Jó 36

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR)

1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,

2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,

3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,

4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́;

5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn;

6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,

7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,

8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà,

9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,

10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,

11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,

12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,

13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;

14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,

15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,

16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,

17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;

18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;

19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?

20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké

21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú,

22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;

23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,

24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,

25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;

26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,

27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,

28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,

29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,

30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká

31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;

32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì

33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jó 36, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.