1 “Ṣe bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmarè fún ìdájọ́?
2 Wọ́n a sún àmì ààlà ilẹ̀,
3 Wọ́n á sì da kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní baba lọ,
4 Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà,
5 Kíyèsi i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó nínú ijù ni àwọn tálákà jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
6 Olúkúlùkù a sì sá ọkà oúnjẹ ẹran rẹ̀ nínú oko,
7 Ní ìhòhò ni wọn máa sùn láìní aṣọ,
8 Ọ̀wààrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,
9 Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò ní ẹnu ọmú,
10 Wọ́n rìn kiri ní ìhòhò láìní aṣọ;
11 Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínú àgbàlá wọn,
12 Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,
13 “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí ìmọ́lẹ̀,
14 Apànìyàn a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,
15 Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró kí ilẹ̀ ṣú díẹ̀;
16 Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,
17 Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀ fún gbogbo wọn;
18 “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi;
19 Gẹ́gẹ́ bi ọ̀dá àti òru ní í mú omi òjò-dídì yọ́,
20 Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀,
21 Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn
22 Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára,
23 Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un,
24 A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ;
25 “Ǹjẹ́, bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ nísinsin yìí, ta ni yóò mú mi ní èké,