1 Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,
2 “A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?
3 Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?
4 Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí,
5 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,
6 kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ,
7 “Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?
8 Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?
9 Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,
10 “Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà
11 Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;
12 Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n
13 “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,
14 bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù
15 nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,
16 Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ;
17 Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,
18 Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;
19 Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,
20 Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;