Números 26
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs VC
1 Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
1 Depois desse flagelo disse o Senhor a Moisés e a Eleazar, filho do sacerdote Aarão:
2 “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
2 "Fazei o recenseamento de toda a assembléia dos israelitas da idade de vinte anos para cima, família por família, todos os que estiverem em condições de pegar em armas."
3 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
3 Moisés e o sacerdote Eleazar disseram pois nas planícies de Moab, às margens do Jordão, perto de Jericó:
4 “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.”
4 "Serão recenseados todos os que tiverem a idade de vinte anos para cima, como o Senhor ordenou a Moisés e aos israelitas ao saírem do Egito.
5 Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli,
5 Rubem primogênito de Israel, Filhos de Rubem: de Henoc, a família dos henoquitas; de Falu, a família dos faluítas;
6 ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni;
6 de Hesron, a família dos hesronitas; de Carmi, a família dos carmitas.
7 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (43,730).
7 Estas são as famílias dos rubenitas; seus recenseados foram em número de 43.730.
8 Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
8 Filho de Falu, Eliab.
9 àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
9 Filhos de Eliab Namuel, Datã e Abiron. Estes são Datã e Abiron, aqueles membros do conselho que se tinham sublevado contra Moisés e Aarão, com os cúmplices de Coré em revolta contra o Senhor.
10 Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba (250) ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
10 A terra, abrindo sua boca, engoliu-os com Coré, enquanto o seu grupo perecia pelo fogo que devorou os duzentos e cinqüenta homens. Isso serviu de exemplo.
11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
11 Os filhos de Coré, porém, não pereceram.
12 Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn:
12 Filhos de Simeão, classificados por famílias: de Namuel, a família dos namuelitas; de Jamim, a família dos jaminitas; de Joaquim, a família dos joaquinitas;
13 ti Sera, ìdílé Sera;
13 de Zaré, a família dos zaritas; de Saul, a família dos saulitas.
14 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba (22,200) ọkùnrin.
14 Tais são as famílias dos simeonitas: 22.200 homens.
15 Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn:
15 Filhos de Gad, classificados por famílias: de Sefon, a família dos sefonitas; de Agi, a família dos agitas; de Sunit, a família dos sunitas;
16 ti Osni, ìdílé Osni;
16 de Ozni, a família dos oznitas; de Her, a família dos heritas;
17 ti Arodi, ìdílé Arodi;
17 de Arod, a família dos aroditas; de Ariel, a família dos arielitas.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (40,500).
18 Estas são as famílias dos gaditas. Seus recenseados foram 40.500.
19 Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
19 Filhos de Judá: Her e. Onã, que morreram na terra de Canaã.
20 Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
20 Eis os filhos de Judá, classificados por famílias: de Sela, a família dos selitas; de Farés, a família dos faresitas; de Zara, a família dos zaritas.
21 Àwọn ọmọ Peresi:
21 Os filhos de Farés foram: de Hesron a família dos hesronitas; de Hamul, a família dos hamulitas.
22 Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (76,500).
22 Tais são as famílias de Judá; seus recenseados foram 76.500.
23 Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
23 Filhos de Issacar, classificados por famílias: de Tola, a família dos tolaítas; de Fua, a família dos fuaítas;
24 ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu;
24 de Jasub, a família dos jasubitas; de Semrã, a família dos semranitas.
25 Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún (64,300).
25 Estas são as famílias de Issacar; seus recenseados foram 64.300.
26 Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
26 Filhos de Zabulon, classificados por famílias: de Sared, a família dos sareditas; de Elon, a família dos elonitas; de Jalel, a família dos jalelitas.
27 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (60,500).
27 Estas são as famílias de Zabulon; seus recenseados foram 60.500.
28 Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
28 Filhos de José, classificados por famílias: Manassés e Efraim.
29 Àwọn ọmọ Manase:
29 Filhos de Manassés: de Maquir, a família dos maquiritas. Maquir gerou Galaad; de Galaad, a família dos galaaditas.
30 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi:
30 Eis os filhos de Galaad: de Jezer, a família dos jezeritas; de Helec, a família dos helequitas;
31 àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli;
31 de Asriel, a família dos asrielitas; de Sequém, a família dos sequemitas;
32 àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida;
32 de Semida, a família dos semidaítas; de Hefer, a família dos heferitas.
33 (Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
33 Salafaad, filho, de Hefer, não teve filhos, mas muitas filhas. Eis os nomes das filhas de Salafaad: Maala Noa, Hegla, Melca e Tersa.
34 Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin (52,700).
34 Estas são as famílias de Manassés; seus recenseados foram 52.700.
35 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
35 Eis os filhos de Efraim classificados por famílias: de Sutala, a família dos sutalaítas; de Bequer, a família dos bequeritas; de Teen, a família dos teenitas.
36 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi:
36 Eis os filhos de Sutala: de Herã, a família dos heranitas.
37 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (32,500).
37 Estas são as famílias dos filhos de Efraim; seus recenseados foram 32.500. Estes são os filhos de José, classificados por famílias.
38 Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí:
38 Filhos de Benjamim, classificados por famílias: de Bela, a família dos belaítas; de Asbel a família dos asbelitas; de Airão, a família dos airamitas;
39 ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu;
39 de Sufão, a família dos sufamitas; de Hufão, a família dos hufamitas.
40 Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí:
40 Os filhos de Bela foram Hered e Noemã; de Hered, a família dos hereditas; de Noemã, a família dos noemanitas.
41 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ (45,600).
41 Tais são os filhos de Benjamim, classificados por famílias; seus recenseados foram em número de 45.600.
42 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
42 Eis os filhos de Dã, classificados por famílias: de Suã, a família dos suamitas. Tais são as famílias de Dã, classificadas por famílias.
43 Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó (64,400).
43 Total das famílias dos suamitas: seus recenseados foram 64.400.
44 Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
44 Filhos de Aser, classificados por famílias: de Jemna, a família dos jemnaítas; de Jessui, a família dos jesuítas; de Bria, a família dos briaítas;
45 Ti àwọn ọmọ Beriah:
45 de Heber, a família dos heberitas; de Melquiel, a família dos melquielitas.
46 (Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
46 O nome da filha de Aser era Sara.
47 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje (53,400).
47 Tais são as famílias dos filhos de Aser; seus recenseados foram 53.400.
48 Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
48 Filhos de Neftali, classificados por famílias: de Jesiel, a família dos jesielitas; de Guni, a família dos gunitas;
49 ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri;
49 de Jeser, a família dos jeseritas; de Selem, a família dos selemitas.
50 Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje (45,400).
50 Estas são as famílias de Neftali classificadas por famílias; seus recenseados foram 45.400.
51 Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin (601,730).
51 Eis o total dos israelitas recenseados: 601.730.
52 Olúwa sọ fún Mose pé,
52 O Senhor disse a Moisés:
53 “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
53 "A terra será dividida entre estes, segundo o número de suas pessoas, para que eles a possuam como herança.
54 Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
54 Aos mais numerosos darás uma parte maior, e aos que forem menos, uma menor; cada um receberá uma parte proporcional ao número dos recenseados.
55 Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
55 Todavia, é a sorte que decidirá a divisão da terra. Eles receberão a sua parte segundo os nomes das tribos patriarcais.
56 Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
56 A propriedade será dividida por sorte entre os grupos numerosos e os grupos menores.
57 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:
57 Eis os levitas recenseados segundo suas famílias: de Gérson, a família dos gersonitas; de Caat, a família dos caatitas; de Merari, a família dos meraritas.
58 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi;
58 Eis as famílias de Levi: a família dos lobnitas, a dos hebronitas, a dos moolitas, a dos musitas, a dos coritas. {Caat gerou Amrão,
59 orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
59 cuja mulher se chamava Jocabed, filha de Levi, nascida no Egito. Ela deu a Amrão: Aarão, Moisés e Maria, sua irmã.
60 Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
60 Aarão teve os filhos: Nadab, Abiú, Eleazar e ltamar.
61 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
61 Nadab e Abiú morreram quando apresentaram diante do Senhor um fogo estranho.}
62 Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún (23,000). Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
62 Recenseados os levitas, todos os varões da idade de um mês para cima somaram 23.000. Não foram contados no recenseamento dos israelitas, porque não se lhes havia destinado nenhum patrimônio no meio deles.
63 Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
63 Tal é o recenseamento dos israelitas que fizeram Moisés e o sacerdote Eleazar nas planícies de Moab, às margens do Jordão, perto de Jericó.
64 Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
64 Não se achou entre eles nenhum daqueles que tinham sido recenseados antes por Moisés e Aarão no deserto do Sinai,
65 Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.
65 porque o Senhor dissera deles: "Morrerão no deserto." Não ficou nenhum deles, exceto Caleb, filho de Jefoné, e Josué, filho de Nun.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Números 26, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.