Jeremias 27

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
1 No início do reinado de Zedequias, o filho de Josias, rei de Judá, veio esta palavra a Jeremias, da parte do SENHOR, dizendo:
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
2 Assim me diz o SENHOR: Faze para ti atilhos e jugos, e coloque-os sobre o teu pescoço.
3 Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
3 E envie-os para o rei de Edom, e para o rei de Moabe, e para o rei dos amonitas, e para o rei de Tiro, e para o rei de Sidom, por meio da mão dos mensageiros que chegam a Jerusalém até Zedequias, rei de Judá.
4 Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
4 E ordena-lhes que digam aos seus senhores: Assim diz o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel: Assim direis a vossos senhores:
5 Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
5 Eu fiz a terra, o homem e os animais que estão sobre o chão, por meu grande poder, e por meu braço estendido, e a tenho dado a quem me parece adequado.
6 Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
6 E agora eu dei todas estas terras na mão de Nabucodonosor, o rei de Babilônia, meu servo. E também lhe dei todos os animais, para o servirem.
7 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
7 E todas as nações lhe servirão, e ao seu filho, e ao filho do seu filho, até que venha o tempo da sua terra. E então muitas nações e grandes reis se servirão dele.
8 “ ‘ “Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
8 E acontecerá que, a nação e o reino que não vier a servir a Nabucodonosor, o rei de Babilônia, e que não colocar seus pescoços sob o jugo do rei de Babilônia, esta nação eu punirei, diz o SENHOR, com a espada, e com a fome, e com a peste, até eu os ter consumido pela sua mão.
9 Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
9 Portanto não escuteis a vossos profetas, nem a vossos adivinhadores, nem a vossos sonhadores, nem a vossos encantadores, nem a vossos feiticeiros, os quais vos falam, dizendo: Vós não servireis o rei de Babilônia.
10 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
10 Porque eles vos profetizam uma mentira, para retirar-vos da vossa terra, e eu vos lançarei dela, e perecereis.
11 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.” ’ ”
11 Porém as nações que trouxerem seus pescoços sob o jugo do rei de Babilônia, e o servirem, estas deixarei permanecer na sua própria terra, diz o SENHOR. E eles a cultivarão, e nela habitarão.
12 Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
12 Eu também falei a Zedequias, rei de Judá, conforme todas estas palavras, dizendo: Trazei vossos pescoços sob o jugo do rei de Babilônia, e servi-o, e a seu povo e vivereis.
13 Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
13 Por que morrereis, tu e teu povo, pela espada, pela fome, e pela peste, como o SENHOR falou contra a nação que não servir ao rei de Babilônia?
14 Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
14 Portanto, não escuteis as palavras dos profetas que vos falam, dizendo: Vós não servireis ao rei de Babilônia, pois eles vos profetizam uma mentira.
15 ‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’ ”
15 Porque eu não lhes enviei, diz o SENHOR, contudo eles profetizam uma mentira em meu nome, para que eu vos afugente, e para que vós venhais a perecer, vós, e os profetas que profetizam para vós.
16 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
16 Também eu falei para os sacerdotes e para todo este povo, dizendo: Assim diz o SENHOR: Não escuteis as palavras de vossos profetas que profetizam para vós, dizendo: Eis que os vasos da casa do SENHOR agora cedo serão trazidos novamente de Babilônia, porque eles vos profetizam mentira.
17 Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
17 Não os escuteis; servi ao rei de Babilônia e vivei. Por que razão deveria esta cidade ser devastada?
18 Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
18 Porém se eles são profetas, e se a palavra do SENHOR está com eles, deixe-os agora fazer intercessão ao SENHOR dos Exércitos, para que os vasos que são deixados na casa do SENHOR, e n a casa do rei de Judá, e em Jerusalém, não sejam levados para a Babilônia.
19 Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
19 Porque assim diz o SENHOR dos Exércitos a respeito das colunas, e a respeito do mar, e a respeito das bases, e a respeito do restante dos vasos que restam nesta cidade;
20 Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
20 os quais Nabucodonosor, rei de Babilônia, não tomou, quando ele levou cativos de Jerusalém para Babilônia a Jeconias, filho de Jeoiaquim, rei de Judá, e todos os nobres de Judá e Jerusalém.
21 Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
21 Sim, assim diz o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel, a respeito dos vasos que restam dentro da casa do SENHOR, e dentro da casa do rei de Judá, e de Jerusalém:
22 ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’ ”
22 Eles serão carregados para Babilônia, e lá eles estarão até o dia em que eu os visitar, diz o SENHOR. Então eu os trarei para cima, e restituí-los-eis para este lugar.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jeremias 27, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.