Ezequiel 26
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs NTLH
1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
1 No ano décimo primeiro do nosso cativeiro , no primeiro dia do mês, o Senhor falou comigo de novo. Ele disse:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
2 — Homem mortal , o povo da cidade de Tiro está se alegrando por causa de uma coisa. Eles estão gritando: “Jerusalém, a nossa rival no comércio, está arrasada! As suas portas se abriram para nós entrarmos, e com a sua derrota nós vamos enriquecer!”
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
3 — Agora, o que eu, o Senhor Deus, estou dizendo é isto: Cidade de Tiro, eu estou contra você. Vou trazer muitas nações para lutarem contra você, e elas virão como as ondas do mar.
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
4 Elas destruirão as muralhas da sua cidade e derrubarão as suas torres. Aí eu varrerei o pó e deixarei a rocha nua.
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
5 Os pescadores estenderão as redes para secarem em cima dela, ali no mar , onde se encontra. Sou eu, o Senhor Deus, quem está falando. As nações vão atacar e roubar Tiro
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 e com as suas espadas vão matar aqueles que vivem nas cidades que estão perto, em terra firme. Aí a cidade de Tiro ficará sabendo que eu sou o Senhor .
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
7 O Senhor Deus diz: — Eu vou trazer da Babilônia o rei Nabucodonosor, o mais poderoso de todos os reis, para atacar Tiro. Ele virá do Norte com um forte exército, com cavalos e carros de guerra e com cavalaria.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
8 Aqueles que vivem perto, nas cidades que estão em terra firme, serão mortos na batalha. O inimigo cavará trincheiras, fará rampas de ataque e levantará um muro de escudos contra você.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
9 Com máquinas de lançar pedras, eles derrubarão as suas muralhas e com barras de ferro derrubarão as suas torres.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
10 Os seus cavalos levantarão nuvens de pó que cobrirão vocês. Quando eles passarem pelos portões da cidade conquistada, o barulho dos cavalos deles puxando carretas e carros de guerra fará tremer as suas muralhas.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
11 Os cavaleiros deles invadirão as suas ruas, matando o seu povo à espada. As suas fortes colunas serão jogadas no chão.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
12 Os seus inimigos roubarão as suas riquezas e as suas mercadorias. Derrubarão as suas muralhas e arrasarão as suas casas luxuosas. Eles jogarão no mar as pedras, a madeira e o entulho.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
13 Acabarei com as suas canções e farei parar a música das suas liras .
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
14 De você só deixarei uma rocha nua, onde os pescadores estenderão as redes para secarem. A cidade nunca mais será reconstruída. Eu, o Senhor Deus, estou falando.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
15 O Senhor Deus diz isto à cidade de Tiro: — Quando você for conquistada, o povo que vive no litoral ficará apavorado com os gritos daqueles que forem feridos de morte.
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
16 Todos os reis das nações do litoral descerão dos seus tronos. Tirarão os seus mantos e as suas roupas bordadas e, tremendo de medo, sentarão no chão. Quando virem o que aconteceu com você, eles terão tanto pavor, que ficarão tremendo sem parar.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé:
17 Eles cantarão para você este cântico fúnebre: “A cidade famosa está destruída! Os seus navios foram varridos dos mares. O povo desta cidade dominava os mares e metia medo em todos os que viviam no litoral.
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì
18 Agora, no dia em que a cidade caiu, as ilhas estão tremendo, e os seus moradores estão apavorados com tanta destruição.”
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
19 O Senhor Deus diz: — Farei você virar uma cidade deserta como as cidades arrasadas, onde não mora ninguém. Cobrirei você com as águas profundas do mar.
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
20 Eu a jogarei no mundo dos mortos , onde você estará com gente que morreu há muito tempo. E a abandonarei nesse mundo que fica debaixo da terra, nesse país de ruínas antigas, e você ficará junto com os mortos. Em você, Tiro, nunca mais morará ninguém, e você não voltará a ocupar o seu lugar no mundo dos vivos.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
21 Farei de você um exemplo horrível, e esse será o seu fim. As pessoas vão procurá-la, mas ninguém a encontrará. Eu, o Senhor Deus, falei.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 26, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.