Ezequiel 26
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs NAA
1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
1 No décimo primeiro ano, no primeiro dia do mês, a palavra do Senhor veio a mim, dizendo:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
2 — Filho do homem, Tiro disse a respeito de Jerusalém: “Bem feito! Foi arrombada a porta dos povos; ela se abriu para mim. Eu me tornarei rico, agora que ela foi arrasada.”
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
3 Por isso, assim diz o Senhor Deus: Eis que eu estou contra você, ó Tiro, e farei subir muitas nações contra você, assim como o mar faz subir as suas ondas.
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
4 Elas destruirão as muralhas de Tiro e derrubarão as suas torres; e eu varrerei o seu pó e farei dela uma rocha escalvada.
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
5 No meio do mar, ela virá a ser apenas um lugar onde pescadores secam as suas redes, porque eu o anunciei, diz o Senhor Deus. E ela se tornará despojo para as nações.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Suas filhas que estão no continente serão mortas à espada; e saberão que eu sou o Senhor .
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
7 — Porque assim diz o Senhor Deus: Eis que trarei contra Tiro o rei Nabucodonosor, que virá da Babilônia, do Norte, e que é o rei dos reis. Ele virá com cavalos e carros de guerra, com cavaleiros e com um enorme exército.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
8 As suas filhas que estão no continente, ele as matará à espada. Construirá torres de ataque e levantará uma rampa contra você; virá com uma barreira de escudos.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
9 Disporá os seus aríetes contra as suas muralhas e, com barras de ferro, derrubará as suas torres.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
10 Os cavalos dele serão tantos que você ficará coberta de pó. As suas muralhas tremerão com o estrondo dos cavaleiros, das carretas e dos carros de guerra, quando ele entrar pelos seus portões como quem entra numa cidade em que se fez uma brecha na muralha.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
11 Com os cascos dos seus cavalos, socará todas as suas ruas. Matará o seu povo à espada, e as suas fortes colunas cairão por terra.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
12 Roubarão as suas riquezas e saquearão as suas mercadorias. Derrubarão as suas muralhas e arrasarão as suas casas luxuosas. As suas pedras, a sua madeira e o seu pó eles lançarão no meio das águas.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
13 Farei cessar o ruído das suas canções, e não se ouvirá mais o som das suas harpas.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
14 Farei de você uma rocha escalvada. Você virá a ser apenas um lugar onde pescadores secam as suas redes. Você jamais será reconstruída, porque eu, o Senhor , falei, diz o Senhor Deus.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
15 — Assim diz o Senhor Deus a Tiro: “Não é fato que as terras do mar tremerão com o estrondo da sua queda, quando gemerem os feridos, quando se fizer espantosa matança em suas ruas?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
16 Todos os príncipes do mar descerão dos seus tronos, tirarão de si os seus mantos e despirão as suas roupas bordadas. Eles se vestirão de tremores, ficarão sentados no chão, tremendo sem parar; e ficarão espantados por causa de você.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé:
17 Farão uma lamentação sobre você, dizendo: ‘Como você está destruída, ó bem-povoada e afamada cidade, que dominava os mares, você e os seus moradores, que atemorizavam todos os que moram ali!
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì
18 Agora as ilhas tremem, no dia da sua queda; as ilhas, que estão no mar, ficam assustadas com a sua ruína.’”
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
19 — Porque assim diz o Senhor Deus: “Quando eu fizer de você uma cidade arrasada, como as cidades que não são habitadas, quando eu fizer o abismo vir sobre você e as muitas águas a cobrirem,
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
20 então farei você descer com os que descem à cova, ao povo antigo. Eu a farei habitar nas partes mais baixas da terra, em lugares desertos antigos, com os que descem à cova, para que você não seja mais habitada; e criarei coisas gloriosas na terra dos viventes.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
21 Farei de você um grande espanto, e você deixará de existir; quando a procurarem, você jamais será encontrada”, diz o Senhor Deus.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 26, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.