Ezequiel 25
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
1 A palavra do SENHOR veio novamente a mim, dizendo:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
2 Filho do homem, direciona a tua face contra os amonitas, e profetiza contra eles.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
3 E dize aos amonitas: Ouvi a palavra do Senhor DEUS: Assim diz o Senhor DEUS: Porquanto tu disseste: Ah! contra o meu santuário, quando foi profanado; e contra a terra de Israel, quando foi assolada; e contra a casa de Judá, quando foi ao cativeiro;
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
4 portanto, eis que eu te entregarei aos homens do leste por possessão, e eles estabelecerão seus palácios em ti, e farão suas moradas em ti; eles comerão os teus frutos, e eles beberão o teu leite.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
5 E eu farei de Rabá um estábulo para camelos, e dos amonitas um lugar de encontro de rebanhos; e vós sabereis que eu sou o SENHOR.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
6 Porque assim diz o Senhor DEUS: Porque aplaudiste com as tuas mãos, e pateaste com os pés, e te regozijaste no coração com todo o despeito contra a terra de Israel,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”
7 portanto, eis que eu estenderei a minha mão sobre ti, e te entregarei por despojo aos pagãos, e te cortarei fora dos povos, e te farei perecer fora das nações; eu te destruirei; e tu saberás que eu sou o SENHOR.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
8 Assim diz o Senhor DEUS: Porquanto Moabe e Seir dizem: Eis que a casa de Judá é como todos os pagãos.
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
9 Portanto, eis que eu abrirei o lado de Moabe desde as cidades, desde as suas cidades que estão nas suas fronteiras, a glória da nação, Bete-Jesimote, Baal-Meom, e Quiriataim.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
10 Aos homens do leste com os amonitas, e os darei por possessão, para que os amonitas não possam ser lembrados entre as nações.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”
11 E eu executarei juízos sobre Moabe, e eles saberão que eu sou o SENHOR.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
12 Assim diz o Senhor DEUS: Porquanto aquele Edom tratou contra a casa de Judá levando a vingança, e grandemente se ofendeu, e se vingou sobre eles.
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
13 Portanto, assim diz o Senhor DEUS: Eu também estenderei a minha mão sobre Edom, e cortarei fora dela homem e animal, e eu a assolarei desde Temã, e aqueles de Dedã cairão pela espada.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’ ”
14 E eu deitarei a minha vingança sobre Edom, pela mão do meu povo, Israel; e eles farão em Edom de acordo com a minha fúria e segundo o meu furor; e eles conhecerão a minha vingança, diz o Senhor DEUS.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
15 Assim diz o Senhor DEUS: Porquanto os filisteus trataram através da vingança, e fizeram vingança com um coração despeitado, para destruí-la por causa do ódio antigo.
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
16 Portanto, assim diz o Senhor DEUS: Eis que eu estenderei a minha mão sobre os filisteus, e eu cortarei fora os quereteus, e destruirei os remanescentes da costa do mar.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.” ’ ”
17 E eu executarei grande vingança sobre eles, com furiosas repreensões, e eles saberão que eu sou o SENHOR, quando eu deitar minha vingança sobre eles.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 25, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.