Zacarias 1
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
1 No oitavo mês, no segundo ano de Dario, veio a palavra do SENHOR a Zacarias, filho de Baraquias, filho de Ido, o profeta, dizendo:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
2 O SENHOR se irou fortemente contra vossos pais.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
3 Portanto, dize-lhes: Assim diz o SENHOR dos Exércitos: Tornai-vos para mim, diz o SENHOR dos Exércitos, e tornarei para vós, diz o SENHOR dos Exércitos.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
4 Não sejais como vossos pais, aos quais os primeiros profetas clamavam, dizendo: Assim diz o SENHOR dos Exércitos: Desviai-vos agora dos vossos maus caminhos, e das vossas más obras; mas eles não ouviram, nem me escutaram, diz o SENHOR.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
5 Vossos pais, onde estão eles? E os profetas, vivem eles para sempre?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín?
6 Mas as minhas palavras e os meus estatutos, os quais ordenei aos meus servos, os profetas, não alcançaram os vossos pais? E eles voltaram e disseram: Assim como o SENHOR dos Exércitos pensou em fazer a nós, de acordo com os nossos caminhos, e segundo as nossas obras, assim ele tratou conosco.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
7 Aos vinte e quatro dias do décimo primeiro mês, que é o mês de Sebate, no segundo ano de Dario, veio a palavra do SENHOR a Zacarias, filho de Baraquias, filho de Ido, o profeta, dizendo:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
8 Eu vi à noite, e eis que vi um homem que cavalgava sobre um cavalo vermelho, e ele se pôs entre as murtas que estavam abaixo; e atrás dele havia cavalos vermelhos, salpicados e brancos.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?”
9 Então eu disse: Ó meu senhor, o que são estes? E o anjo que falava comigo me disse: Eu te mostrarei o que estes são.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
10 E o homem que estava entre as murtas respondeu e disse: Estes são os que o SENHOR enviou para percorrerem a terra para lá e para cá.
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
11 E eles responderam ao anjo do SENHOR, que estava entre as murtas, e disseram: Nós já percorremos a terra, para lá e para cá, e eis que toda a terra está tranquila e em descanso.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
12 Então o anjo do SENHOR respondeu e disse: Ó SENHOR dos Exércitos, até quando não terás misericórdia de Jerusalém e das cidades de Judá, contra as quais estiveste indignado estes setenta anos?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
13 E o SENHOR respondeu ao anjo que falava comigo com palavras boas e palavras consoladoras.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
14 Então o anjo que falava comigo disse-me: Clama, dizendo: Assim diz o SENHOR dos Exércitos: Eu zelo por Jerusalém e por Sião com mui grande zelo.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
15 E estou muito descontente com os pagãos que estão em descanso; porque eu estava um pouco descontente, mas eles ajudaram a espalhar a aflição.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
16 Portanto, assim diz o SENHOR: Eu voltei a Jerusalém com misericórdias; minha casa será edificada nela, diz o SENHOR dos Exércitos, e um cordel será estendido sobre Jerusalém;
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’ ”
17 clama outra vez, dizendo: Assim diz o SENHOR dos Exércitos: As minhas cidades, através da prosperidade, ainda se espalharão; e o SENHOR ainda consolará Sião e ainda escolherá Jerusalém.
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
18 Então eu levantei os meus olhos, e eis que vi quatro chifres.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?”
19 E disse ao anjo que falava comigo: Que são estes? E ele me respondeu: Estes são os chifres que dispersaram a Judá, a Israel e a Jerusalém.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
20 E o SENHOR me mostrou quatro carpinteiros.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?”
21 Então eu disse: Que vêm estes fazer? E ele falou, dizendo: Estes são os chifres que dispersaram Judá, de modo que nenhum homem ergueu a sua cabeça; estes, pois, vieram para amedrontá-los, para derrubar os chifres dos gentios, que levantaram o seu chifre sobre a terra de Judá para dispersá-la.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Zacarias 1, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.