Números 3

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
1 Estas são também as gerações de Arão e de Moisés, no dia em que o SENHOR falou com Moisés, no monte Sinai.
2 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari.
2 E estes são os nomes dos filhos de Arão: Nadabe, o primogênito, e Abiú, Eleazar e Itamar.
3 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
3 Estes são os nomes dos filhos de Arão, os sacerdotes que foram ungidos, a quem ele consagrou para ministrar o sacerdócio.
4 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
4 E Nadabe e Abiú morreram perante o SENHOR, quando ofereceram fogo estranho perante o SENHOR, no deserto do Sinai; e não tiveram filhos; e Eleazar e Itamar ministraram o sacerdócio diante de Arão, seu pai.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
5 E o SENHOR falou a Moisés, dizendo:
6 “Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́.
6 Traze a tribo de Levi, e apresenta-os perante o sacerdote Arão, para que possam servi-lo.
7 Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
7 E cumprirão as suas obrigações, e as obrigações de toda a congregação, diante do tabernáculo da congregação, para fazer o serviço do tabernáculo.
8 Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
8 E cuidarão de todos os instrumentos do tabernáculo da congregação, e cuidarão dos filhos de Israel, para realizar o serviço do tabernáculo.
9 Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.
9 E darás os levitas a Arão e seus filhos; eles lhe serão dados, de entre os filhos de Israel.
10 Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
10 E nomearás a Arão e seus filhos, e eles exercerão as funções sacerdotais; e o estranho que se aproximar morrerá.
11 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
11 E o SENHOR falou a Moisés, dizendo:
12 “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi,
12 E eis que tomei os levitas do meio dos filhos de Israel, em lugar de todo o primogênito, que abre a madre entre os filhos de Israel; e os levitas serão meus.
13 nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
13 Porque meus são todos os primogênitos; porque no dia em que feri todos os primogênitos na terra do Egito, santifiquei para mim todos os primogênitos de Israel, tanto humanos como animais, e serão meus; eu sou o SENHOR.
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
14 E o SENHOR falou a Moisés, no deserto do Sinai, dizendo:
15 “Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
15 Conta os filhos de Levi, segundo a casa de seus pais, conforme as suas famílias; contarás todos os homens com idade igual ou superior a um mês.
16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
16 E Moisés os contou, segundo a palavra do SENHOR, como ele ordenara.
17 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi:
17 E estes eram os filhos de Levi, por seus nomes: Gérson, e Coate, e Merari.
18 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni:
18 E estes são os nomes dos filhos de Gérson, por suas famílias: Libni e Simei.
19 Àwọn ìdílé Kohati ni:
19 E os filhos de Coate, por suas famílias: Anrão, e Izar, e Hebrom, e Uziel.
20 Àwọn ìdílé Merari ni:
20 E os filhos de Merari, por suas famílias: Mali e Musi; estas são as famílias dos levitas, segundo a casa de seus pais.
21 Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
21 De Gérson era a família dos libnitas e a família dos simeítas; estas são as famílias dos gersonitas.
22 Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (7,500).
22 Os que foram contados entre eles, segundo o número de todos os homens, de idade igual e superior a um mês de idade, os que foram contados entre eles, eram sete mil e quinhentos.
23 Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
23 As famílias dos gersonitas acamparão atrás do tabernáculo, no lado do ocidente.
24 Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
24 E o capitão da casa do pai dos gersonitas será Eliasafe, o filho de Lael.
25 Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
25 E o cargo dos filhos de Gérson no tabernáculo da congregação, será o tabernáculo, e a tenda, e a sua coberta, e a cortina para a porta do tabernáculo da congregação,
26 aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
26 e as cortinas do átrio, e a cortina para a porta do átrio, que está ao lado do tabernáculo, e ao redor do altar, e também as suas cordas, para todo o seu serviço.
27 Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
27 E de Coate era a família dos anramitas, e a família dos izaritas, e a família dos hebronitas, e a família dos uzielitas; estas são as famílias dos coatitas.
28 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta (8,600),
28 O número de todos os homens, com idade igual ou superior a um mês, era oito mil e seiscentos cuidando da guarda do santuário.
29 Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
29 As famílias dos filhos de Coate acamparão do lado sul do tabernáculo.
30 Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
30 E o capitão da casa do pai das famílias dos coatitas será Elisafã, filho de Uziel.
31 Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
31 E eles deverão cuidar da arca, e da mesa, e do castiçal, e dos altares, e dos utensílios do santuário, com que servem, e a cortina, e todo o serviço.
32 Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
32 E Eleazar, o filho de Arão, o sacerdote, será o capitão dos capitães dos levitas, e supervisor dos que terão o cuidado do santuário.
33 Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
33 De Merari era a família dos malitas e a família dos musitas; estas são as famílias de Merari.
34 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n (6,200).
34 E os que foram contados entre eles, segundo o número de todos os homens com idade igual ou superior a um mês, eram seis mil e duzentos.
35 Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili.
35 E o chefe da casa do pai das famílias de Merari será Zuriel, filho de Abiail; e eles acamparão do lado norte do tabernáculo.
36 Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn.
36 E sob a custódia e cargo dos filhos de Merari estarão as tábuas do tabernáculo, e os varais, e as colunas, e as bases, e todos os seus utensílios, e todo o seu serviço,
37 Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
37 e as colunas do átrio ao redor, e suas bases, e suas estacas, e suas cordas.
38 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé.
38 Mas os que acampam diante do tabernáculo, no lado oriental, diante do tabernáculo da congregação, no lado oriental, Moisés, e Arão e seus filhos manterão a guarda do santuário para o cargo dos filhos de Israel; e o estranho que se aproximar, morrerá.
39 Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún (22,000).
39 Todos os que foram contados dos levitas, que Moisés e Arão contaram, por ordem do SENHOR, segundo suas famílias, todos os homens com idade igual ou superior a um mês, eram vinte e dois mil.
40 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
40 E o SENHOR disse a Moisés: Conta todos os primogênitos dos filhos de Israel, com idade igual ou superior a um mês, e toma o número de seus nomes.
41 Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
41 E tomarás os levitas para mim (eu sou o SENHOR), no lugar de todos os primogênitos dos filhos de Israel, e o gado dos levitas, no lugar dos primogênitos entre o gado dos filhos de Israel.
42 Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
42 E Moisés contou, como o SENHOR lhe ordenara, todos os primogênitos entre os filhos de Israel.
43 Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ọ̀rìnlúgba ó dín méje (22,273).
43 E todos os primogênitos, pelos números de nomes, com idade igual ou superior a um mês, dos que foram contados, somaram vinte e dois mil e duzentos e setenta e três.
44 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
44 E o SENHOR falou a Moisés, dizendo:
45 “Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa.
45 Toma os levitas, no lugar de todos os primogênitos entre os filhos de Israel, e o gado dos levitas, no lugar do gado de Israel, e os levitas serão meus: eu sou o SENHOR.
46 Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje (273) àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ,
46 E para aqueles que serão resgatados dos duzentos e setenta e três, dos primogênitos dos filhos de Israel, que são em maior número que os levitas,
47 ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera.
47 tomarás por cabeça cinco shekels, segundo o shekel do santuário os tomarás; (o shekel é vinte geras).
48 Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.”
48 E darás a Arão e aos seus filhos o dinheiro com o qual o número deles será resgatado.
49 Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà.
49 E Moisés tomou o dinheiro do resgate daqueles que eram em maior número que eles, que foram resgatados pelos levitas.
50 Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùndínlógójì (1,365) gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli.
50 Dos primogênitos dos filhos de Israel, ele tomou o dinheiro; mil trezentos e sessenta e cinco shekels, segundo o shekel do santuário.
51 Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
51 E Moisés deu o dinheiro dos que foram resgatados a Arão e a seus filhos, segundo a palavra do SENHOR, conforme o SENHOR ordenara a Moisés.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Números 3, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.