Malaquias 2
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín.
1 E agora, ó sacerdotes, este mandamento é para vós.
2 Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.
2 Se não ouvirdes, e se não o colocardes no vosso coração, para dar glória ao meu nome, diz o SENHOR dos Exércitos, eu enviarei uma maldição sobre vós, e eu amaldiçoarei as vossas bênçãos; sim, já as tenho amaldiçoado, porque não o colocais em vossos corações.
3 “Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀.
3 Eis que eu corromperei a vossa semente, e espalharei esterco sobre as vossas faces, até o esterco das vossas festas solenes; e alguém vos retirará com ele.
4 Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 E sabereis que eu enviei este mandamento a vós, para que o meu pacto pudesse ser com Levi, diz o SENHOR dos Exércitos.
5 “Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á.
5 Meu pacto com ele foi de vida e de paz, e eu lha dei pelo temor com o qual ele me temia, e temeu diante do meu nome.
6 Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
6 A lei da verdade estava em sua boca, e a iniquidade não se achou nos seus lábios; ele andava comigo em paz e em retidão, e desviou muitos da iniquidade.
7 “Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
7 Porque os lábios do sacerdote devem guardar o conhecimento, e eles devem buscar a lei em sua boca, porque ele é o mensageiro do SENHOR dos Exércitos.
8 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
8 Mas vós vos desviastes do caminho; vós fizestes muitos tropeçarem na lei; tendes corrompido o pacto de Levi, diz o SENHOR dos Exércitos.
9 “Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”
9 Portanto eu também vos tenho feito desprezíveis, e vis diante de todo o povo, visto que não guardastes os meus caminhos, mas fostes parciais na lei.
10 Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?
10 Não temos nós todos um mesmo pai? Não nos criou um mesmo Deus? Por que agimos traiçoeiramente, cada homem contra o seu irmão, profanando o pacto de nossos pais?
11 Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó.
11 Judá tem agido traiçoeiramente, e uma abominação se cometeu em Israel e em Jerusalém; pois Judá tem profanado a santidade do SENHOR, a qual ele ama, e se casou com a filha de um deus estranho.
12 Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
12 O SENHOR cortará dos tabernáculos de Jacó o homem que fizer isto, o mestre e o estudioso, e o que oferece uma oferta ao SENHOR dos Exércitos.
13 Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe. Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín.
13 E fazeis isto novamente, cobrindo o altar do SENHOR com lágrimas, com choro e com gemidos; de tal modo que não mais considera a oferta, nem a recebe com boa vontade de tua mão.
14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.
14 Ainda dizeis: Por quê? Porque o SENHOR tem sido testemunha entre ti e a esposa da tua juventude, contra a qual tens agido traiçoeiramente, sendo ela a tua companheira, e a esposa do teu pacto.
15 Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.
15 E não fez ele somente um? Ainda que ele possuísse o restante do espírito. E por que somente um? Para que ele pudesse buscar uma semente piedosa. Portanto tome cuidado com o seu espírito, e ninguém aja traiçoeiramente contra a esposa da sua juventude.
16 “Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” se ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
16 Pois o SENHOR, o Deus de Israel, diz que ele odeia o repúdio, e aquele que encobre a violência com a sua roupa, diz o SENHOR dos Exércitos; portanto, atentai em vosso espírito, e não ajais traiçoeiramente.
17 Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara.
17 Tendes cansado o SENHOR com vossas palavras; e ainda dizeis: Em que o temos cansado? Quando vós dizeis: Todo o que faz o mal é bom à vista do SENHOR, e ele se deleita desses; ou, onde está o Deus do juízo?
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Malaquias 2, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.