Levítico 15
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
1 E o SENHOR falou a Moisés e a Arão, dizendo:
2 “Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
2 Falai aos filhos de Israel, e dizei-lhes: Quando algum homem tem um corrimento do seu membro viril, por causa do seu problema, ele é impuro.
3 Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
3 E esta será a norma sobre a impureza pelo seu corrimento: seja o seu membro viril emitir um corrimento, ou que esteja obstruído pelo seu corrimento, será impuro.
4 “ ‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
4 Toda cama em que se deitar o que tiver corrimento será impuro; e toda coisa sobre o que se assentar será impura.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
5 E qualquer que tocar a sua cama lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
6 E aquele que se assentar sobre alguma coisa em que se assentou o que tem o corrimento lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
7 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
7 E aquele que tocar a carne do que tem o corrimento lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
8 “ ‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
8 E se aquele que tem o corrimento cuspir sobre aquele que é limpo, então ele lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
9 “ ‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
9 E toda sela em que cavalgar o que tem o corrimento será impura.
10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
10 E qualquer que tocar em alguma coisa que estava debaixo dele será impuro até a tarde; e aquele que levar qualquer destas coisas lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
11 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
11 E todo aquele a quem tocar o que tem o corrimento, sem ter lavado as suas mãos com água, ele lavará as suas vestes, e se banhará em água, e será impuro até a tarde.
12 “ ‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
12 E o vaso de barro em que tocar o que tem o corrimento será quebrado; e todo vaso de madeira será lavado com água.
13 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
13 E quando o que tem o corrimento estiver limpo do seu corrimento, então ele contará sete dias para a sua purificação; e lavará as suas vestes, e banhará a sua carne em água corrente, e será limpo.
14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
14 E no oitavo dia, ele tomará duas rolas, ou dois pombinhos, e virá perante o SENHOR, à porta do tabernáculo da congregação, e os dará ao sacerdote;
15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
15 e o sacerdote os oferecerá, um para a oferta pelo pecado e o outro para oferta queimada; e o sacerdote fará expiação para ele, diante do SENHOR, por causa do seu corrimento.
16 “ ‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
16 E se a semente de cópula de algum homem sair dele, então banhará toda a sua carne com água e será impuro até a tarde.
17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
17 E toda veste, e toda pele em que houver semente da cópula será lavada com água, e serão impuras até a tarde.
18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
18 E a mulher com quem um homem se deitar com semente da cópula, ambos se banharão com água, e serão impuros até a tarde.
19 “ ‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
19 E se a mulher tiver um corrimento, e o seu corrimento na sua carne for sangue, ela será separada por sete dias, e qualquer que a tocar será impuro até a tarde.
20 “ ‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
20 E toda coisa sobre o que ela se deitar durante a sua separação será impuro; e tudo sobre o que ela se assentar será impuro.
21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
21 E qualquer que tocar a sua cama lavará as suas vestes, e se banhará com água, e será impuro até a tarde.
22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
22 E qualquer que tocar alguma coisa sobre o que ela se tiver assentado lavará as suas vestes, e se banhará com água, e será impuro até a tarde.
23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
23 E se alguma coisa estiver sobre sua cama ou sobre alguma coisa em que ela se assentou, se alguém a tocar, será impuro até a tarde.
24 “ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
24 E se algum homem se deitar com ela, e a sua menstruação verter sobre ele, impuro será por sete dias; também toda cama sobre a qual se deitar será impura.
25 “ ‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
25 E se uma mulher tiver um corrimento do seu sangue por muitos dias fora do tempo da sua separação, ou quando tiver fluxo de sangue por mais tempo do que a sua separação; todos os dias do corrimento da sua impureza será como nos dias da sua separação; ela será impura.
26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
26 Toda cama sobre a qual ela se deitar todos os dias do seu corrimento lhe será como a cama da sua separação; e tudo sobre o qual ela se assentar será impura, conforme a impureza da sua separação.
27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
27 E aquele que tocar estas coisas será impuro, e lavará as suas vestes, e se banhará com água, e será impuro até a tarde.
28 “ ‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
28 Mas se ela for limpa do seu corrimento, então ela contará para si sete dias, e depois ela será limpa.
29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
29 E no oitavo dia ela tomará consigo duas rolas ou dois pombinhos, e os trará ao sacerdote, à porta do tabernáculo da congregação.
30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
30 Então o sacerdote oferecerá um por oferta pelo pecado, e o outro por oferta queimada; e o sacerdote fará expiação por ela perante o SENHOR, pelo corrimento da sua impureza.
31 “ ‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’ ”
31 Assim separareis os filhos de Israel das suas impurezas, para que eles não morram nas suas impurezas, quando corromperem o meu tabernáculo, que está no meio deles.
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
32 Esta é a lei daquele que tem o corrimento e daquele de quem sai a semente, e que assim fica impuro;
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.
33 e daquela que está enferma no seu período menstrual, e daquele que tem o corrimento, do homem, e da mulher, e daquele que se deitar com aquela que está impura.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Levítico 15, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.