Juízes 21
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
1 Ora, os homens de Israel haviam jurado em Mispá, dizendo: Nenhum de nós dará a sua filha como esposa a Benjamim.
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
2 E o povo chegou à casa de Deus, e ali permaneceu até o anoitecer diante de Deus, e ergueu a sua voz, e chorou amargamente;
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
3 e disse: Ó SENHOR Deus de Israel, por que isto se sucedeu em Israel, que hoje deveria haver uma tribo faltante em Israel?
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
4 E sucedeu que, pela manhã, o povo se levantou cedo, e ali erigiu um altar, e ofereceu ofertas queimadas e ofertas de paz.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
5 E os filhos de Israel disseram: Quem há dentre todas as tribos de Israel que não subiu com a congregação até o SENHOR? Pois eles haviam feito um juramento solene acerca daquele que não subisse até o SENHOR em Mispá, dizendo: Este, certamente, será levado à morte.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
6 E os filhos de Israel se arrependeram no lugar de Benjamim, o seu irmão, e disseram: Há uma tribo cortada de Israel neste dia.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
7 Como providenciaremos esposas para aqueles que restam, já que juramos pelo SENHOR que não lhes daremos as nossas filhas por esposas?
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
8 E eles disseram: Qual das tribos de Israel não subiu até o SENHOR em Mispá? E eis que ninguém de Jabes-Gileade havia vindo à assembleia.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
9 Pois o povo estava contado e, eis que não havia ali nenhum dos habitantes de Jabes-Gileade.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà (12,000) àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
10 E a congregação enviou para lá doze mil homens dos mais valentes e lhes ordenou, dizendo: Ide e feri os habitantes de Jabes-Gileade com o fio da espada, com as mulheres e as crianças.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
11 E isto é o que fareis: Vós destruireis por completo todos os machos, e toda mulher que tenha se deitado ao lado de homem.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó (400) ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
12 E eles encontraram no meio dos habitantes de Jabes-Gileade quatrocentas virgens, que não haviam conhecido homem pois não se deitaram com nenhum macho; e eles as trouxeram para o acampamento de Siló, que fica na terra de Canaã.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
13 E a congregação inteira mandou alguns falarem aos filhos de Benjamim que estavam na rocha de Rimom, para chamá-los pacificamente.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
14 E Benjamim retornou naquela hora; e lhes deram esposas as quais tinham sido salvas com vida das mulheres de Jabes-Gileade; e mesmo assim elas não lhes foram suficientes.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
15 E o povo se arrependeu no lugar de Benjamim, porque o SENHOR havia feito uma brecha nas tribos de Israel.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
16 Então, os anciãos da congregação disseram: Como providenciaremos esposas para aqueles que restam, já que as mulheres de Benjamim estão destruídas?
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
17 E eles disseram: Deve haver uma herança para eles que escaparam de Benjamim, para que uma tribo de Israel não seja destruída.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’ ”
18 Todavia, não podemos dar-lhes esposas dentre as nossas filhas; pois os filhos de Israel juraram, dizendo: Maldito seja o que der uma esposa a Benjamim.
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
19 Então, eles disseram: Eis que há uma festa do SENHOR em Siló anualmente, em um lugar que fica no lado norte de Betel, no lado leste da estrada que vai desde Betel até Siquém, e ao sul de Lebona.
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
20 Por isso, eles ordenaram aos filhos de Benjamim, dizendo: Ide e deitai-vos em espera nos vinhedos;
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
21 e vede, e eis que, se as filhas de Siló vierem dançar em danças, então saí dos vinhedos, e cada um dos vossos homens pegue a sua esposa dentre as filhas de Siló, e ide para a terra de Benjamim.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’ ”
22 E será que, quando os seus pais ou os seus irmãos vierem até nós para se queixarem, nós lhes diremos: Sede-lhes favoráveis por nossa causa; porque não reservamos para cada homem a sua esposa na guerra; pois vós não lhas destes neste momento, para que vós não sejais culpados.
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
23 E os filhos de Benjamim assim o fizeram, e tomaram esposas para si, segundo o seu número, daquelas que dançaram, as quais eles pegaram: e eles foram e retornaram para a sua herança, e reformaram as cidades, e nelas habitaram.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
24 E os filhos de Israel partiram dali naquela hora, cada homem para a sua tribo e para a sua família, e dali saiu cada qual para a sua herança.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
25 Naqueles dias não havia rei em Israel; cada homem fazia aquilo que era certo aos seus próprios olhos.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Juízes 21, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.