Josué 4
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
1 E sucedeu que, quando todo o povo terminou de atravessar o Jordão, o SENHOR falou a Josué, dizendo:
2 “Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
2 Tomai doze homens do povo, um homem de cada tribo,
3 kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’ ”
3 e ordenai-lhes, dizendo: Tomai daqui do meio do Jordão, do lugar onde os pés dos sacerdotes permaneceram firmes, doze pedras, e carregai-as convosco, e deixai-as no alojamento, onde vos alojareis esta noite.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
4 Então, Josué chamou os doze homens, aos quais havia preparado dentre os filhos de Israel, um homem de cada tribo;
5 ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
5 e Josué lhes disse: Passai diante da arca do SENHOR, vosso Deus, para o meio do Jordão e tomai, cada um de vós, uma pedra sobre o ombro, segundo o número das tribos dos filhos de Israel;
6 kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
6 para que isso possa ser um sinal no meio de vós, para que quando os vossos filhos perguntarem aos pais nos tempos vindouros, dizendo: O que significam para vós estas pedras?
7 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
7 Então responder-lhes-eis, que as águas do Jordão foram repartidas diante da arca do pacto do SENHOR; quando ela passou pelo Jordão, as águas do Jordão foram repartidas, e estas pedras serão para sempre um memorial para os filhos de Israel.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
8 E os filhos de Israel fizeram segundo Josué lhes ordenou, e tomaram doze pedras do meio do Jordão, tal como o SENHOR falara a Josué, segundo o número das tribos dos filhos de Israel, e as carregaram até o lugar onde eles se alojaram, e lá as puseram.
9 Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
9 E Josué posicionou doze pedras no meio do Jordão, no lugar onde os pés dos sacerdotes que carregaram a arca do pacto estiveram; e elas estão lá até este dia.
10 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
10 Pois os sacerdotes que carregavam a arca ficaram no meio do Jordão, até que tudo o que o SENHOR ordenou a Josué que falasse ao povo tivesse terminado, segundo tudo o que Moisés ordenou a Josué; e o povo se apressou e atravessou.
11 bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
11 E sucedeu que, quando todo o povo terminou de atravessar, a arca do SENHOR atravessou, e os sacerdotes, na presença do povo.
12 Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
12 E atravessaram os filhos de Rúben, e os filhos de Gade, e a meia tribo de Manassés, armados diante dos filhos de Israel, tal como Moisés lhes tinha falado;
13 Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì (40,000) tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
13 cerca de quarenta mil, preparados para a guerra, passaram adiante do SENHOR para a batalha, nas planícies de Jericó.
14 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
14 Naquele dia o SENHOR exaltou Josué à vista de todo Israel; e eles o temeram, como temeram a Moisés, todos os dias da sua vida.
15 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
15 E o SENHOR falou a Josué, dizendo:
16 “Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
16 Ordena aos sacerdotes que carregam a arca do testemunho, para que saiam do Jordão.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
17 Josué, portanto, ordenou aos sacerdotes, dizendo: Saiam do Jordão.
18 Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
18 E sucedeu que, quando os sacerdotes que carregavam a arca do pacto do SENHOR haviam subido do meio do Jordão, e as solas dos pés dos sacerdotes foram erguidas para a terra seca, as águas do Jordão retornaram para o seu lugar, e fluíram por sobre todas as suas margens, tal como faziam antes.
19 Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
19 E o povo subiu do Jordão no décimo dia do primeiro mês, e acampou em Gilgal, na fronteira leste de Jericó.
20 Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
20 E aquelas doze pedras, que eles retiraram do Jordão, Josué levantou-as em Gilgal.
21 Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
21 E ele falou aos filhos de Israel, dizendo: Quando os vossos filhos perguntarem aos seus pais em tempos vindouros, dizendo: O que significam estas pedras?
22 Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
22 Então fareis saber a vossos filhos, dizendo: Israel veio através deste Jordão em terra seca.
23 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
23 Pois o SENHOR, vosso Deus, secou as águas do Jordão diante de vós, até que tivésseis atravessado, assim como o SENHOR, vosso Deus, fez no mar Vermelho, o qual ele secou diante de nós, até que o tivéssemos atravessado.
24 Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”
24 Para que todos os povos da terra pudessem conhecer a mão do SENHOR, que é poderosa; para que vós pudésseis temer ao SENHOR, vosso Deus, para sempre.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Josué 4, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.