Josué 23

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
1 E sucedeu que, muito tempo depois do ­SENHOR ter dado repouso para Israel de todos os seus inimigos ao redor, Josué tornou-se velho e acometido pela idade.
2 Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
2 E Josué convocou todo o Israel, e os seus anciãos, e os seus cabeças, e os seus juízes, e os seus oficiais, e lhes disse: Sou velho e acometido pelos anos;
3 Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
3 e vós vistes tudo o que o ­SENHOR, vosso Deus, fez a todas estas nações por causa de vós; pois o ­SENHOR, vosso Deus, é quem tem lutado por vós.
4 Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
4 Vede que dividi para vós, por sorte, estas nações que restam, como herança para as vossas tribos, desde o Jordão, com todas as nações que extirpei, até o grande mar em direção ao oeste.
5 Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
5 E o ­SENHOR, vosso Deus, ele as expelirá de diante de vós, e as expulsará da vossa vista; e vós possuireis a sua terra, como o ­SENHOR, vosso Deus, vos tem prometido.
6 “Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
6 Sede, portanto, muito corajosos, em guardar e fazer tudo o que está escrito no livro da lei de Moisés, para que daí não vos desvies para a direita, nem para a esquerda;
7 Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
7 para que não vades no meio destas nações, estas que permanecem no meio de vós; nem façais menção do nome dos seus deuses, nem por eles façais jurar, nem os sirvais, tampouco a eles vos curveis;
8 Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
8 mas, apegai-vos ao ­SENHOR, vosso Deus, como fizestes até este dia.
9 “Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
9 Pois o ­SENHOR expulsou de diante de vós, grandes e fortes nações; porém quanto a vós, nenhum homem foi capaz de ficar de pé diante de vós até este dia.
10 Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún (1,000) ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
10 Um homem de vós perseguirá a mil; pois o ­SENHOR, vosso Deus, ele é quem luta por vós, como vos ­prometeu.
11 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
11 Portanto, atentai bem a vós mesmos, para que ameis o ­SENHOR, vosso Deus.
12 “Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
12 Porém, se de alguma maneira vos voltardes, e vos unirdes ao remanescente destas nações, a saber, estas que permanecem no meio de vós, e com elas celebrardes casamentos, e entrardes a elas, e elas a vós;
13 Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
13 saibais com certeza que o ­SENHOR, vosso Deus, não mais expelirá nenhuma destas nações de diante de vós; mas elas serão laços e armadilhas para vós, e flagelos nos vossos lombos, e espinhos nos vossos olhos, até que pereçais desta boa terra que o ­SENHOR vosso Deus vos deu.
14 “Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
14 E eis que neste dia estou seguindo pelo caminho de toda a terra; e saibais, em todos os vossos corações e em todas as vossas almas, que não falhou nenhuma das boas coisas que o ­SENHOR, vosso Deus, falou a respeito de vós; todas sucederam a vós, e nenhuma delas falhou.
15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
15 Portanto, sucederá que, tal como as coisas boas vos sobrevieram, as quais o ­SENHOR, vosso Deus, vos prometeu; também o ­SENHOR trará sobre vós todas as coisas más, até que tenha vos destruído desta boa terra que o ­SENHOR, vosso Deus, vos deu.
16 Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”
16 Quando tiverdes transgredido o pacto do ­SENHOR, vosso Deus, o qual ele vos ordenou, e tiverdes ido servir a outros deuses, e a eles vos inclinardes; então a ira do SENHOR se acenderá contra vós, e perecereis rapidamente da boa terra que ele vos deu.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Josué 23, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.