Josué 18
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
1 E toda a congregação dos filhos de Israel se reuniu em Siló, e ali montaram o tabernáculo da congregação. E a terra estava subjugada diante deles.
2 ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
2 E ali permaneciam, entre os filhos de Israel, sete tribos que ainda não haviam recebido a sua herança.
3 Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
3 E Josué disse aos filhos de Israel: Quanto tempo vos descuidareis de ir para possuir a terra que o SENHOR Deus dos vossos pais vos deu?
4 Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
4 Separai dentre vós três homens de cada tribo e eu os enviarei, e eles se levantarão e andarão através da terra, e a descreverão segundo a sua herança, e eles retornarão a mim.
5 Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
5 E eles a dividirão em sete partes: Judá habitará no seu termo meridional, e a casa de José habitará nos seus termos setentrionais.
6 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
6 Vós, portanto, descrevereis a terra em sete partes, e traze-me para cá a descrição, a fim de que, aqui eu possa lançar sorte por vós diante do SENHOR nosso Deus.
7 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
7 Porém, os levitas não têm qualquer parte no meio de vós, pois o sacerdócio do SENHOR é a sua herança; e Gade, e Rúben, e a meia tribo de Manassés, receberam a sua herança além do Jordão, no leste, a qual lhes deu Moisés, o servo do SENHOR.
8 Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
8 E os homens se levantaram, e partiram; e Josué incumbiu os que seguiram de descreverem a terra, dizendo: Ide e andai através da terra, e a descrevei, e retornai a mim para que, aqui eu possa lançar sorte por vós diante do SENHOR em Siló.
9 Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
9 E os homens partiram e percorreram a terra, e a descreveram por cidades, em sete partes, num livro, e retornaram até Josué, ao exército em Siló.
10 Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
10 E Josué lançou sorte por eles em Siló diante do SENHOR; e ali Josué dividiu a terra para os filhos de Israel, segundo as suas divisões.
11 Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
11 E surgiu a sorte da tribo dos filhos de Benjamim, segundo as suas famílias; e o termo da sua sorte seguia no meio dos filhos de Judá e dos filhos de José.
12 Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
12 E o limite do lado norte era desde o Jordão; e o limite subia até o lado de Jericó no lado norte, e subia através dos montes, em direção oeste; e as suas saídas ficavam no deserto de Bete-Áven.
13 Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
13 E o limite seguia desde lá até Luz, para o lado de Luz, que é Betel, na direção sul; e o limite descia até Atarote-Adar, próximo ao outeiro que se situa no lado sul da baixa Bete-Horom.
14 Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
14 E o limite se estendia de lá, e rodeava o canto do mar em direção sul, desde o outeiro que se situa diante de Bete-Horom, na direção sul; e as suas saídas estavam em Quiriate-Baal, que é Quiriate-Jearim, uma cidade dos filhos de Judá; esta era a porção ocidental.
15 Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
15 E a porção meridional era desde a extremidade de Quiriate-Jearim, e o limite saía no oeste, e seguia até o poço das águas de Neftoa;
16 Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
16 e o limite descia até o extremo do monte que se situa diante do vale do filho de Hinom, e que está no vale dos gigantes no norte, e desceram ao vale de Hinom, para o lado dos jebuseus ao sul, e descia a En-Rogel,
17 Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
17 e se estendia desde o norte, e seguia até En-Semes, e prosseguia em direção a Gelilote, que está no outro lado da subida de Adumim, e descia até a pedra de Boã, o filho de Rúben,
18 Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
18 e passava em direção ao lado oposto de Arabá, em direção norte, e descia até Arabá;
19 Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
19 e o limite passava até o lado de Bete-Hogla, na direção norte; e as saídas do limite ficavam na baía norte do mar salgado, na extremidade meridional do Jordão; este era o termo meridional.
20 Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn.
20 E o Jordão era o seu limite no lado leste. Esta foi a herança dos filhos de Benjamim, pelos seus limites em redor, segundo as suas famílias.
21 Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí:
21 Ora, as cidades da tribo dos filhos de Benjamim, segundo as suas famílias eram: Jericó, e Bete-Hogla, e o vale de Queziz,
22 Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
22 e Bete-Arabá, e Zemaraim, e Betel,
23 Affimu, Para, Ofira
23 e Avim, e Pará, e Ofra,
24 Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
24 e Quefar-Amonai, e Ofni, e Gaba: doze cidades com as suas aldeias;
25 Gibeoni, Rama, Beeroti,
25 Gibeão, e Ramá, e Beerote,
26 Mispa, Kefira, Mosa,
26 e Mispá, e Cefira, e Mosa,
27 Rekemu, Irpeeli, Tarala,
27 e Requém, e Irpeel, e Tarala,
28 Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn.
28 e Zela, e Elefe, e Jebus, que é Jerusalém, Gibeá, e Quiriate: catorze cidades com as suas aldeias. Esta é a herança dos filhos de Benjamim, segundo as suas famílias.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Josué 18, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.