Josué 14
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
1 E estas são as regiões que os filhos de Israel herdaram na terra de Canaã, as quais Eleazar, o sacerdote, e Josué, o filho de Num, e os cabeças dos pais das tribos dos filhos de Israel, lhes distribuíram por herança.
2 Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
2 Por sorte foi a sua herança, como o SENHOR ordenou pela mão de Moisés, para as nove tribos, e para a meia tribo.
3 Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
3 Pois Moisés tinha dado a herança das duas tribos e da meia tribo no outro lado do Jordão; mas para os levitas ele não deu nenhuma herança no meio deles.
4 Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
4 Porque os filhos de José eram duas tribos, Manassés e Efraim; portanto eles não deram parte aos levitas na terra, salvo cidades para habitarem, com os seus arredores para o seu gado e para seus bens.
5 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
5 Como o SENHOR ordenou a Moisés, assim fizeram os filhos de Israel, e dividiram a terra.
6 Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
6 Então os filhos de Judá vieram até Josué em Gilgal; e Calebe, o filho de Jefoné, o quenezeu, disse-lhe: Tu sabes o que o SENHOR disse a Moisés, o homem de Deus, em Cades-Barneia acerca de mim e de ti.
7 Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
7 Quarenta anos tinha eu, quando Moisés, o servo do SENHOR, enviou-me de Cades-Barneia para espionar a terra; e eu lhe trouxe de volta uma palavra conforme esta estava no meu coração.
8 ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
8 Contudo, os meus irmãos que comigo subiram fizeram derreter o coração do povo, mas eu segui com integridade o SENHOR, meu Deus.
9 Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
9 E Moisés jurou naquele dia, dizendo: Certamente a terra sobre a qual os teus pés pisaram será a tua herança, e dos teus filhos para todo o sempre, porque tu seguiste com integridade o SENHOR meu Deus.
10 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
10 E agora eis que o SENHOR tem me mantido vivo, como declarou, nestes quarenta e cinco anos, verdadeiramente, desde que o SENHOR falou esta palavra a Moisés, enquanto os filhos de Israel vagavam pelo deserto; e agora, vê que nestes dias já tenho oitenta e cinco anos.
11 Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
11 Como ainda sou tão forte nestes dias como era no dia em que Moisés me enviou; como antes era a minha força, assim também é a minha força agora, para a guerra, tanto para sair, como para entrar.
12 Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
12 Agora, portanto, dá-me este monte, do qual o SENHOR falou naquele dia, pois tu ouviste naquele dia que os anaquins lá estavam, e que as cidades eram grandes e fortificadas; se assim for, o SENHOR estará comigo, e eu serei capaz de expulsá-los, como disse o SENHOR.
13 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
13 E Josué o abençoou, e deu Hebrom a Calebe, o filho de Jefoné, por herança.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
14 Hebrom, portanto, tornou-se a herança de Calebe, o filho de Jefoné, o quenezeu, até este dia, porque ele seguiu com integridade o SENHOR, Deus de Israel.
15 (Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.)
15 E antes o nome de Hebrom era Quiriate-Arba; sendo que Arba fora um homem afamado entre os anaquins. E a terra teve repouso da guerra.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Josué 14, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.