Josué 13
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
1 Ora, Josué era velho e acometido pelos anos; e o SENHOR lhe disse: Tu és velho e acometido pelos anos, e ainda resta muitíssima terra para ser possuída.
2 “Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù:
2 Esta é a terra que ainda permanece: todos os limites dos filisteus, e toda a Gesur,
3 láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni;
3 de Sior, que está diante do Egito, até os limites de Ecrom, em direção norte, que é considerada dos cananeus; cinco senhores dos filisteus, os gazitas, e os asdoditas, os ascalonitas, os gititas, e os ecronitas; também os aveus;
4 láti gúúsù;
4 desde o sul, toda a terra dos cananeus, e Meara que está ao lado dos sidônios, até Afeque, aos limites dos amorreus;
5 àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali;
5 e a terra dos gebalitas e todo o Líbano, em direção a nascente do sol, desde Baal-Gade, debaixo do monte Hermom até a entrada de Hamate.
6 “Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
6 Todos os habitantes da região alta, desde o Líbano, até Misrefote-Maim, e todos os sidônios, eu os expulsarei de diante dos filhos de Israel; basta dividi-la em porções aos israelitas, por herança, tal como eu te ordenei.
7 pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
7 Agora, portanto, divide esta terra por herança para as nove tribos, e para a meia tribo de Manassés.
8 Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
8 Com as quais os rubenitas e os gaditas receberam a sua herança, que Moisés lhes deu, além do Jordão em direção leste, como Moisés, o servo do SENHOR lhes deu;
9 Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
9 desde Aroer, que está na margem do rio Arnom, e a cidade que está no meio do rio, e toda a planície de Medeba até Dibom;
10 Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
10 e todas as cidades de Seom, rei dos amorreus, que reinaram em Hesbom, até os limites dos filhos de Amom;
11 Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
11 e Gileade, e os limites dos gesureus e dos maacateus, e todo o monte Hermom, e toda a Basã até Salca;
12 ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
12 todo o reino de Ogue em Basã, que reinou em Astarote e em Edrei, que restou do remanescente dos gigantes; pois estes Moisés feriu, e os expulsou.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
13 Contudo, os filhos de Israel não expulsaram os gesureus, nem os maacateus; mas os gesureus e os maacateus habitam no meio dos Israelitas até este dia.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
14 Somente à tribo de Levi ele não deu herança alguma; os sacrifícios do SENHOR, Deus de Israel, feitos ao fogo são a sua herança, conforme ele lhes declarou.
15 Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
15 E Moisés deu à tribo dos filhos de Rúben, uma herança segundo as suas famílias.
16 láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
16 E o seu termo foi desde Aroer, que está na margem do rio Arnom, e a cidade que está no meio do rio, e toda a planície de Medeba;
17 sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
17 Hesbom, e todas as suas cidades que estão na planície: Dibom, e Bamote-Baal, e Bete-Baal-Meom,
18 Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
18 e Jaza, e Quedemote, e Mefaate,
19 Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
19 e Quiriataim, e Sibma, e Zerete-Saar, no monte do vale,
20 Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
20 e Bete-Peor, e Asdote-Pisga, e Bete-Jesimote,
21 gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
21 e todas as cidades da planície, e todo o reino de Seom, rei dos amorreus, que reinou em Hesbom, ao qual Moisés feriu, com os príncipes de Midiã, Evi, e Requém, e Zur, e Hur, e Reba, os quais eram xeiques de Seom, habitantes da região.
22 Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
22 Também os filhos de Israel mataram à espada Balaão, filho de Beor, o adivinho, que estava dentre os que foram mortos por eles.
23 Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
23 E os limites dos filhos de Rúben eram o Jordão e os seus limites. Esta foi a herança dos filhos de Rúben, segundo as suas famílias, suas cidades e aldeias.
24 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 E Moisés deu herança à tribo de Gade, aos filhos de Gade segundo as suas famílias.
25 Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
25 E o seu termo era Jazer, e todas as cidades de Gileade, e a metade da terra dos filhos de Amom, até Aroer que está diante de Rabá;
26 àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
26 e desde Hesbom até Ramate-Mispá e Betonim, e de Maanaim até os termos de Debir;
27 àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
27 e no vale, Bete-Arã, e Bete-Ninra, e Sucote, e Zafom, e o restante do reino de Seom, rei de Hesbom, Jordão e o seu termo, até a beira do Mar de Quinerete, no outro lado do Jordão, na direção leste.
28 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
28 Esta é a herança dos filhos de Gade, segundo as suas famílias, cidades e aldeias.
29 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 E Moisés deu herança para a meia tribo de Manassés; e esta foi a possessão da meia tribo dos filhos de Manassés, segundo as suas famílias.
30 Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
30 E o seu termo era desde Maanaim, todo o Basã, todo o reino de Ogue, rei de Basã, e todas as aldeias de Jair, que estão em Basã, sessenta cidades;
31 ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani).
31 e a metade de Gileade, e Astarote, e Edrei, cidades do reino de Ogue em Basã, eram pertencentes aos filhos de Maquir, o filho de Manassés, à metade dos filhos de Maquir, segundo as suas famílias.
32 Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
32 Estas são as regiões que Moisés distribuiu por herança nas planícies de Moabe, no outro lado do Jordão, junto a Jericó, na direção leste.
33 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
33 Mas para a tribo de Levi, Moisés não deu herança alguma; o SENHOR, Deus de Israel, era a sua herança, conforme ele lhes dissera.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Josué 13, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.