Jeremias 36
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
1 E aconteceu que, no quarto ano de Jeoiaquim, o filho de Josias, rei de Judá, que esta palavra veio até Jeremias da parte do SENHOR, dizendo:
2 “Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
2 Toma o rolo de um livro, e escreve neste todas as palavras que eu tenho falado para ti contra Israel, e contra Judá, e contra todas as nações, desde o dia em que eu te falei, desde os dias de Josias, até este dia.
3 Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
3 Pode ser que a casa de Judá ouça todo o mal que eu planejo fazer-lhes, para que eles possam se converter, cada homem de seu mau caminho, para que eu possa perdoar a sua iniquidade e o seu pecado.
4 Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
4 Então Jeremias chamou Baruque, o filho de Nerias. E Baruque escreveu, da boca de Jeremias, todas as palavras do SENHOR, que ele lhe tinha falado, sobre o rolo de um livro.
5 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
5 E Jeremias ordenou a Baruque, dizendo: Eu estou encarcerado, eu não posso ir à casa do SENHOR.
6 Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
6 Portanto, vai tu, aos ouvidos do povo, na casa do SENHOR, no dia do jejum, e lê no rolo que escrevestes da minha boca, as palavras do SENHOR. E também tu as lerás aos ouvidos de todo o Judá, que vem de suas cidades.
7 Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
7 Pode ser que eles venham a apresentar a sua súplica perante o SENHOR, e retornem cada um de seu mau caminho, pois grande é a ira e a fúria que o SENHOR tem manifestado contra este povo.
8 Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
8 E Baruque, o filho de Nerias, fez conforme tudo o que Jeremias, o profeta, lhe ordenou, lendo no livro as palavras do SENHOR, na casa do SENHOR.
9 Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
9 E aconteceu no quinto ano de Jeoiaquim, o filho de Josias, rei de Judá, no mês nono, que eles proclamaram um jejum perante o SENHOR para todo o povo em Jerusalém, e para todo o povo que veio das cidades de Judá para Jerusalém.
10 Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
10 Então Baruque leu no livro as palavras de Jeremias, na casa do SENHOR, na câmara de Gemarias, o filho de Safã, o escriba, no átrio superior, à entrada do portão novo da casa do SENHOR, aos ouvidos de todo o povo.
11 Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
11 Quando Micaías, o filho de Gemarias, o filho de Safã, ouviu do livro todas as palavras do SENHOR;
12 Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
12 então ele desceu em direção à casa do rei, à câmara do escriba. E eis que, todos os príncipes lá estavam: Elisama, o escriba, e Delaías, o filho de Semaías, e Elnatã, o filho de Acbor, e Gemarias, o filho de Safã, e Zedequias, o filho de Hananias, e todos os príncipes.
13 Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
13 Então Micaías declarou-lhes todas as palavras que ouvira, quando Baruque leu o livro aos ouvidos do povo.
14 Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
14 Portanto, todos os príncipes enviaram Jeúdi, o filho de Netanias, o filho de Selemias, o filho de Cusi, a Baruque, dizendo: Toma em tua mão o rolo que leste aos ouvidos do povo, e vem. Então Baruque, o filho de Nerias, tomou o rolo em sua mão, e veio até eles.
15 Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!”
15 E eles lhe disseram: Assenta-te agora, e lê isto aos nossos ouvidos. Então Baruque o leu aos seus ouvidos.
16 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
16 E aconteceu que, ao ouvirem todas as palavras, ficaram temerosos uns para os outros, e disseram a Baruque: Nós certamente contaremos ao rei todas estas palavras.
17 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
17 E eles perguntaram a Baruque, dizendo: Conta-nos agora, como tu escreveste todas estas palavras da sua boca?
18 Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
18 Então Baruque respondeu-lhes: Com sua boca, ele proferiu para mim todas estas palavras, e eu as escrevi com tinta no livro.
19 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
19 Então disseram os príncipes para Baruque: Vai, esconde-te, tu e Jeremias, e não deixeis nenhum homem saber onde vós estais.
20 Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
20 E eles foram ter com o rei no átrio, porém eles deixaram o rolo na câmara de Elisama, o escriba, e anunciaram todas as palavras aos ouvidos do rei.
21 Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
21 Então o rei enviou Jeúdi para que trouxesse o rolo. E ele o tomou de dentro da câmara de Elisama, o escriba. E Jeúdi o leu aos ouvidos do rei, e aos ouvidos de todos os príncipes que estavam junto ao rei;
22 Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
22 então o rei assentou-se na casa de inverno, no mês nono. E havia um fogo na lareira queimando perante ele.
23 Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
23 E aconteceu que quando Jeúdi tinha lido três ou quatro folhas, ele as cortou com um canivete, e lançou-as ao fogo que estava na lareira, até que todo o rolo se consumiu no fogo que estava na lareira.
24 Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
24 Contudo, eles não temeram, nem rasgaram as suas vestes, nem o rei, nem qualquer de seus servos que ouviram todas estas palavras.
25 Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
25 Todavia, Elnatã, e Delaías e Gemarias haviam intercedido ao rei para que ele não queimasse o rolo, porém ele não os ouvira.
26 Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
26 Porém, o rei ordenou Jerameel, o filho de Hameleque, e Seraías, o filho de Azriel, e Selemias, o filho de Abdeel, que capturassem a Baruque, o escriba, e Jeremias, o profeta. Porém o SENHOR os escondeu.
27 Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
27 Então a palavra do SENHOR veio a Jeremias, depois que o rei queimou o rolo, e as palavras que Baruque escreveu da boca de Jeremias, dizendo:
28 “Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
28 Toma novamente outro rolo, e escreve nele todas as palavras anteriores, que estavam no primeiro rolo, que Jeoiaquim o rei de Judá queimou.
29 Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
29 E tu dirás a Jeoiaquim rei de Judá: Assim diz o SENHOR: Tu queimaste este rolo, dizendo: Por que escreveste nele, dizendo: O rei de Babilônia certamente virá e destruirá esta terra, e fará cessar dali homem e animal?
30 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
30 Portanto, assim diz o SENHOR de Jeoiaquim, rei de Judá: Ele não terá ninguém para se assentar sobre o trono de Davi, e seu cadáver será lançado no calor do dia, e na geada da noite.
31 Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’ ”
31 E eu o punirei, e a sua semente, e a seus servos pela sua iniquidade. E eu trarei sobre eles e sobre os habitantes de Jerusalém, e sobre os homens de Judá, todo o mal que proferi contra eles, mas eles não escutaram.
32 Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.
32 Então tomou Jeremias outro rolo e o deu a Baruque, o escriba, o filho de Nerias, que escreveu nele, da boca de Jeremias, todas as palavras do livro que Jeoiaquim, rei de Judá, tinha queimado no fogo, e ainda se lhes acrescentaram muitas palavras semelhantes.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jeremias 36, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.