Jeremias 34
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
1 A palavra que veio a Jeremias da parte do SENHOR, quando Nabucodonosor, rei de Babilônia, e todo o seu exército, e todos os reinos da terra de seu domínio, e todo o povo, lutou contra Jerusalém, e contra todas as suas cidades, dizendo:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
2 Assim diz o SENHOR, o Deus de Israel: Vai e fala a Zedequias, rei de Judá, e dize-lhe: Assim diz o SENHOR: Eis que eu darei esta cidade na mão do rei de Babilônia, e ele a queimará com fogo.
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
3 E tu não escaparás da sua mão, porém certamente serás tomado e entregue na sua mão, e teus olhos observarão os olhos do rei de Babilônia; e ele falará contigo boca a boca, e tu irás para a Babilônia.
4 “ ‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
4 Contudo ouve a palavra do SENHOR, ó Zedequias, rei de Judá. Assim diz o SENHOR de ti: Tu não morrerás pela espada.
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’ ”
5 Porém tu morrerás em paz, e com as incinerações de teus pais, os reis anteriores, que foram antes de ti; assim eles queimarão aromas por ti, e te lamentarão, dizendo: Ah, senhor! Pois eu tenho dito a palavra, diz o SENHOR.
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
6 Então, Jeremias, o profeta, falou todas estas palavras para Zedequias, rei de Judá, em Jerusalém.
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
7 Quando o exército do rei de Babilônia lutou contra Jerusalém, e contra todas as cidades que restavam de Judá, contra Laquis e contra Azeca, porque estas cidades protegidas permaneceram das cidades de Judá.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
8 Esta é a palavra que veio a Jeremias da parte do SENHOR, depois que o rei Zedequias fez um pacto com todo o povo que estava em Jerusalém, para proclamar a sua liberdade.
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
9 Que todo homem deveria deixar seguir livre o seu servo, e todo homem a sua serva, sendo um hebreu ou uma hebreia, para que ninguém se servisse deles, a saber, de um judeu, seu irmão.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
10 Ora, quando todos os príncipes, e todo o povo, que tinha adentrado no pacto, ouviram que cada um deveria deixar ir livre o seu servo, e cada um a sua serva, para que ninguém mais se sirva deles, então eles obedeceram, e os deixaram ir.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
11 Porém depois disso eles se arrependeram, e fizeram retornar os servos e as servas, a quem eles tinham deixado ir livres, e os trouxeram à sujeição como servos e servas.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
12 Portanto a palavra do SENHOR veio a Jeremias da parte do SENHOR, dizendo:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
13 Assim diz o SENHOR, o Deus de Israel: Eu fiz um pacto com vossos pais no dia em que eu os tirei da terra do Egito, da casa de servidão, dizendo:
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
14 Ao final de sete anos deixai ir cada homem a seu irmão, um hebreu, que foi vendido para ti. E quando ele tiver servido a ti seis anos, tu deixarás ir livre. Porém vossos pais não me escutaram, nem inclinaram os seus ouvidos.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
15 E há pouco tornastes, e fizestes o correto à minha vista, ao proclamar liberdade cada homem ao seu próximo. E vós fizestes um pacto perante mim, na casa que é chamada pelo meu nome.
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
16 Todavia tornastes e contaminastes meu nome, e fizestes retornar cada homem a seu servo, e cada homem a sua serva, a quem ele tinha colocado em liberdade conforme a sua vontade, e os trouxeram em sujeição, para vos serem por servos e por servas.
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
17 Portanto assim diz o SENHOR: Vós não tendes escutado a mim, para proclamar liberdade cada um a seu irmão, e cada homem a seu próximo. Eis que eu proclamo uma liberdade para vós, diz o SENHOR, para a espada, para a peste, e para a fome. E eu vos farei ser removidos para todos os reinos da terra.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
18 E eu entregarei os homens que transgrediram o meu pacto, os quais não cumpriram as palavras do pacto que fizeram perante mim, quando cortaram o novilho em duas partes, e passaram entre as suas partes.
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
19 Os príncipes de Judá, e os príncipes de Jerusalém, os eunucos, e os sacerdotes, e todo o povo da terra, os quais passaram entre as partes do novilho.
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
20 Eu os entregarei nas mãos dos seus inimigos, nas mãos daqueles que buscam a sua vida. E seus cadáveres serão por alimento para as aves do céu, e para os animais da terra.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
21 E Zedequias, rei de Judá, e os seus príncipes eu os entregarei nas mãos dos seus inimigos, e nas mãos daqueles que buscam a sua vida, e na mão do exército do rei de Babilônia, que se retirou de vós.
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
22 Eis que eu ordenarei, diz o SENHOR, e os farei retornar a esta cidade; e eles lutarão contra ela, e a tomarão, e a queimarão com fogo. E eu farei das cidades de Judá uma desolação, sem um habitante.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jeremias 34, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.