Jeremias 29

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
1 Ora, estas são as palavras da carta que Jeremias, o profeta, enviou de Jerusalém para o restante dos anciãos que foram levados cativos, e para os sacerdotes, e para os profetas, e para todo o povo a quem Nabucodonosor tinha levado cativo de Jerusalém para Babilônia;
2 Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
2 (depois que saíram de Jerusalém o rei Jeconias, e a rainha, e os eunucos, os príncipes de Judá e Jerusalém, e os carpinteiros, e os ferreiros),
3 Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
3 pela mão de Elasa, o filho de Safã, e Gemarias, o filho de Hilquias (a quem Zedequias, rei de Judá, enviou para Babilônia a Nabucodonosor, rei de Babilônia), dizendo:
4 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
4 Assim diz o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel, para todos que foram levados cativos, que eu deportei de Jerusalém para Babilônia:
5 “Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
5 Constrói casas, e habitai nelas, e plantai jardins, e comei o seu fruto.
6 Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
6 Tomai vós esposas e gerai filhos e filhas, e tomai esposas para vossos filhos, e dai vossas filhas para maridos, para que possam dar à luz filhos e filhas, multiplicai-vos ali e não vos diminuais.
7 Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
7 E buscai a paz da cidade, para onde eu vos fiz transportar em cativeiro, e orai ao SENHOR por ela, porque na sua paz, vós tereis paz.
8 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
8 Porque assim diz o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel: Não vos engane os vossos profetas, e vossos adivinhadores, que estão no meio de vós, nem escutai os vossos sonhos, os quais vós induzis para que sejam sonhados.
9 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
9 Porque eles vos profetizam falsamente em meu nome; eu não os enviei, diz o SENHOR.
10 Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
10 Porque assim diz o SENHOR: Após se completarem setenta anos em Babilônia, eu vos visitarei e cumprirei a minha boa palavra em vós, fazendo-vos retornar para este lugar.
11 Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
11 Porque eu sei os pensamentos que tenho sobre vós, diz o SENHOR, pensamentos de paz, e não de mal, para vos dar o fim que esperais.
12 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
12 Então me invocarei, e ireis, e orareis a mim, e eu vos escutarei.
13 Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
13 E vós buscar-me-eis, e me encontrareis, quando vós procurardes por mim com todo o vosso coração.
14 Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
14 E eu serei encontrado de vós, diz o SENHOR. E eu desviarei vosso cativeiro, e eu vos ajuntarei de todas as nações, e de todos os lugares para onde eu vos levei, diz o SENHOR. E eu vos trarei novamente ao lugar de onde eu vos levei cativo.
15 Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
15 Porque vós dizeis: O SENHOR nos levantou profetas em Babilônia.
16 Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
16 Sabei que assim diz o SENHOR, do rei que se assenta sobre o trono de Davi, e de todo o povo que habita nesta cidade, e de vossos irmãos que não saíram convosco ao cativeiro.
17 bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
17 Assim diz o SENHOR dos Exércitos: Eis que eu enviarei sobre eles a espada, a fome, e a peste, e os farei semelhantes a figos podres, que não podem ser comidos, de tão ruins que são.
18 Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
18 E eu os perseguirei com a espada, com a fome, e com a peste, e os entregarei para serem espalhados para todos os reinos da terra, para serem uma maldição, e um assombro, e um assobio, e uma desonra, no meio de todas as nações para onde eu os levei.
19 Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
19 Porque eles não escutaram as minhas palavras, diz o SENHOR, que eu enviei a eles por meus servos os profetas, madrugando, e enviando-os. Porém vós não escutastes, diz o SENHOR.
20 Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
20 Ouvi vós portanto a palavra do SENHOR, todos vós do cativeiro, a quem eu enviei de Jerusalém para Babilônia.
21 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
21 Assim diz o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel, de Acabe, o filho de Colaías, e de Zedequias, o filho de Maaseias, os quais vos profetizam mentiras em meu nome: Eis que eu os entregarei na mão de Nabucodonosor, rei de Babilônia, e ele os matará perante vossos olhos.
22 Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
22 E deles será levantada uma maldição por todos os cativos de Judá que estão em Babilônia, dizendo: O SENHOR faça a ti como a Zedequias, e como a Acabe, os quais o rei de Babilônia assou no fogo.
23 Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
23 Porque eles cometeram avareza em Israel, e cometeram adultério com as esposas de seus próximos, e falaram palavras mentirosas em meu nome, as quais não ordenei, e eu o sei, e sou uma testemunha, diz o SENHOR.
24 Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
24 Deste modo tu também falarás a Semaías, o neelamita, dizendo:
25 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
25 Assim fala o SENHOR dos Exércitos, o Deus de Israel, dizendo: Porque tu tens enviado cartas em teu nome para todo o povo que está em Jerusalém, e para Sofonias, o filho de Maaseias, o sacerdote, e para todos os sacerdotes, dizendo:
26 ‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
26 O SENHOR te fez sacerdote no lugar de Jeoiada, o sacerdote, para que sejais oficiais na casa do SENHOR, sobre cada homem que está louco, e fez a si mesmo um profeta, para o colocares na prisão e no tronco.
27 Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
27 Agora, portanto, por que não reprovaste a Jeremias de Anatote, o qual faz a si mesmo um profeta para vós?
28 Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’ ”
28 Por isso ele enviou a nós na Babilônia, dizendo: Este cativeiro é longo; constrói casas para vós, e habitai nelas, e plantai jardins, e comei do seu fruto.
29 Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
29 E Sofonias, o sacerdote, leu esta carta aos ouvidos de Jeremias o profeta.
30 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
30 Então veio a palavra do SENHOR a Jeremias, dizendo:
31 “Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
31 Enviai a todos aqueles do cativeiro, dizendo: Assim diz o SENHOR a respeito de Semaías, o neelamita: Porquanto aquele Semaías profetizou para vós, e eu não o enviei, e ele vos fez confiar em uma mentira.
32 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’ ”
32 Portanto assim diz o SENHOR: Eis que eu punirei Semaías, o neelamita, e a sua semente. Ele não terá um homem para habitar no meio deste povo, nem irá ele ver o bem que eu farei ao meu povo, diz o SENHOR, porque ele ensinou a rebelião contra o SENHOR.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jeremias 29, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.