Jeremias 26
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
1 No início do reinado de Jeoiaquim, o filho de Josias, rei de Judá, veio esta palavra da parte do SENHOR, dizendo:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
2 Assim diz o SENHOR: Permanece no átrio da casa do SENHOR, e fala para todas as cidades de Judá, que chegam para adorar na casa do SENHOR, todas as palavras que eu ordenar que lhes digas; não retires uma palavra.
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
3 Se acontecer deles ouvirem, e voltar cada homem do seu mau caminho, que eu possa arrepender-me do mal que eu planejo trazer sobre eles, por causa da maldade dos seus feitos.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
4 E tu lhes dirás: Assim diz o SENHOR: Se vós não me escutardes, para andar na minha lei, que eu tenho colocado perante vós;
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
5 para ouvir as palavras dos meus servos, os profetas, a quem eu vos enviei, tanto madrugando quanto os enviando, porém vós não escutastes,
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’ ”
6 então eu farei esta casa como Siló, e farei desta cidade uma maldição para todas as nações da terra.
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
7 Assim os sacerdotes e os profetas, e todo o povo, ouviram Jeremias falando estas palavras na casa do SENHOR.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
8 Então sucedeu que, quando Jeremias terminou de falar tudo que o SENHOR lhe ordenara falar para todo o povo, os sacerdotes e os profetas e todo o povo, o agarraram, dizendo: Tu certamente morrerás.
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
9 Por que tu profetizaste no nome do SENHOR, dizendo: Esta casa será como Siló, e esta cidade será desolada sem um habitante? E todo o povo estava reunido contra Jeremias na casa do SENHOR.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
10 Quando os príncipes de Judá ouviram estas coisas, subiram da casa do rei para a casa do SENHOR, e assentaram-se na entrada do portão novo da casa do SENHOR.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
11 Então, falaram os sacerdotes e os profetas para os príncipes e para todo o povo, dizendo: Este homem é digno de morte, pois ele profetizou contra esta cidade, como ouvistes com os vossos ouvidos.
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
12 Então, Jeremias falou para todos os príncipes e para todo o povo, dizendo: O SENHOR enviou-me para profetizar contra esta casa e contra esta cidade todas as palavras que vós ouvistes.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
13 Portanto agora emendai vossos caminhos e vossos feitos, e obedecei a voz do SENHOR vosso Deus, e o SENHOR se arrependerá do mal que pronunciou contra vós.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
14 Quanto a mim, eis que eu estou em vossa mão. Fazei comigo como parecer bem e a vós satisfizer.
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
15 Porém, sabei com certeza que, se me matardes, trareis certamente sangue inocente sobre vós, e sobre esta cidade, e sobre os seus habitantes, porque certamente o SENHOR me enviou até vós para falar todas estas palavras aos vossos ouvidos.
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
16 Então disseram os príncipes e todo o povo para os sacerdotes e para os profetas: Este homem não é digno de morte, pois ele nos falou em nome do SENHOR nosso Deus.
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
17 Então levantaram-se alguns dos anciãos da terra, e falaram para toda a assembleia do povo, dizendo:
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
18 Miqueias, o morastita, profetizou nos dias de Ezequias, rei de Judá, e falou para todo o povo de Judá, dizendo: Assim diz o SENHOR dos Exércitos: Sião será arada como um campo, e Jerusalém tornar-se-á em montões, e o monte desta casa como os lugares altos de uma floresta.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
19 Ezequias, rei de Judá, e todo Judá de algum modo o matou? Não temeu ele ao SENHOR, e suplicou ao SENHOR, e o SENHOR não se arrependeu do mal que tinha pronunciado contra eles? Assim nós poderíamos obter grande mal contra nossas almas.
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
20 E também houve um homem que profetizou no nome do SENHOR, Urias, o filho de Semaías, de Quiriate-Jearim, que profetizou contra esta cidade, e contra esta terra, conforme todas as palavras de Jeremias.
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
21 E quando o rei Jeoiaquim, com todos os seus homens poderosos, e todos os príncipes, ouviram as suas palavras, o rei procurou matá-lo. Mas quando Urias ouviu isto, temeu e fugiu, e foi para o Egito.
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
22 E o rei Jeoiaquim enviou homens ao Egito, a saber: Elnatã, filho de Acbor, e alguns homens com ele ao Egito.
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
23 E eles tiraram Urias do Egito, e o trouxeram para o rei Jeoiaquim, que o matou com a espada, e lançou o seu corpo nas sepulturas do povo comum.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
24 Todavia, a mão de Aicão, o filho de Safã, esteve com Jeremias, para que não o entregassem na mão do povo, para matá-lo.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Jeremias 26, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.