Ezequiel 39

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
1 Portanto, tu, filho do homem, profetiza contra Gogue, e dize: Assim diz o Senhor DEUS: Eis que eu estou contra ti, ó Gogue, principal príncipe de Meseque e de Tubal;
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
2 e eu te virarei de volta, e deixarei uma sexta parte de ti, e far-te-ei subir das partes do norte, e te trarei sobre os montes de Israel;
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
3 e eu atingirei o teu arco da tua mão esquerda, e farei com que as tuas flechas caiam da tua mão direita.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
4 Tu cairás sobre os montes de Israel, tu e todas as tuas tropas, e os povos que estão contigo; te entregarei aos pássaros vorazes de todo o tipo, e aos animais do campo para seres devorado.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
5 Tu cairás sobre o campo aberto; porque eu o falei, diz o Senhor DEUS.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
6 E eu enviarei um fogo sobre Magogue, e entre os que habitam descuidadamente nas ilhas; e eles saberão que eu sou o SENHOR.
7 “ ‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
7 Então, eu farei o meu santo nome conhecido no meio do meu povo Israel, e não mais os deixarei poluírem o meu santo nome; e os pagãos saberão que eu sou o SENHOR, o Santo em Israel.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
8 Eis que é vindo e é feito, diz o Senhor DEUS; este é o dia do qual eu tenho falado.
9 “ ‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
9 E aqueles que habitam nas cidades de Israel irão adiante e acenderão e queimarão as armas, tanto os escudos quanto os broquéis, os arcos e as flechas, e bastões de mão, e as lanças; e eles os queimarão com fogo por sete anos;
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
10 de maneira que não tirarão madeira alguma do campo, nem cortarão nada das florestas; porque eles queimarão as armas com fogo; e despojarão aqueles que os despojaram, e roubarão aqueles que os roubaram, diz o Senhor DEUS.
11 “ ‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
11 E acontecerá que, naquele dia, eu darei a Gogue um lugar de sepultura em Israel, o vale dos passageiros no leste do mar; e pararão os narizes dos passageiros, e lá enterrarão Gogue e toda a sua multidão, e lhe chamarão o vale de Hamom-Gogue.
12 “ ‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
12 E a casa de Israel os estará enterrando durante sete meses, para que eles possam limpar a terra.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
13 Sim, todo o povo da terra os enterrará, e será para eles um renome o dia em que eu for glorificado, diz o Senhor DEUS.
14 “ ‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
14 E separarão homens de continuo trabalho, percorrerão a terra, para que eles, juntamente com os que passam, sepultem os que tiverem ficado sobre a face da terra, para limpá-la; durante sete meses farão esta busca.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
15 E os passageiros que passarem pela terra, quando algum deles vir o osso de um homem, então ele colocará um sinal junto a ele, até que os enterradores o tenham enterrado no vale de Hamom-Gogue.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
16 E também o nome da cidade será Hamona. Assim, eles limparão a terra.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
17 E tu, filho do homem, assim diz o Senhor DEUS: Fala a toda ave emplumada, e a cada animal do campo: Reuni-vos e vinde, ajuntai-vos de todo lado para o meu sacrifício, que eu sacrifico por vós, um sacrifício grande sobre os montes de Israel, para que possais comer carne e beber sangue.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
18 Comereis a carne dos poderosos e bebereis o sangue dos príncipes da terra; de carneiros, de cordeiros, e de cabras, e de novilhos, todos os cevados de Basã.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
19 E comereis a gordura até que estejais cheios, e bebereis sangue até que estejais bêbados, do meu sacrifício que eu sacrifiquei por vós.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
20 Assim, sereis fartos à minha mesa com cavalos e carruagens, com homens poderosos, e com todos os homens de guerra, diz o Senhor DEUS.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
21 E eu colocarei a minha glória entre os pagãos, e todos os pagãos verão o meu juízo, que eu executei, e a minha mão, que pus sobre eles.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 Assim a casa de Israel saberá que eu sou o SENHOR seu Deus, daquele dia em diante.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
23 E os pagãos saberão que a casa de Israel foi ao cativeiro por sua iniquidade; porque eles transgrediram contra mim, portanto eu escondi minha face deles, e os entreguei na mão de seus inimigos; então eles caíram todos à espada.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
24 De acordo com a sua impureza, e de acordo com as suas transgressões eu tenho feito a eles, e escondi minha face deles.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
25 Portanto, assim diz o Senhor DEUS: Agora eu trarei novamente o cativeiro de Jacó, e terei misericórdia sobre toda a casa de Israel, e serei ciumento por causa do meu santo nome;
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
26 depois que eles tiverem carregado a sua vergonha, e todas as suas transgressões pelas quais transgrediram contra mim, quando habitaram seguramente em sua terra, e ninguém os deixava temerosos.
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
27 Quando eu os tiver trazido novamente dos povos, e os tiver ajuntado das terras de seus inimigos, e for santificado por eles à vista das muitas nações;
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
28 então, eles saberão que eu sou o SENHOR seu Deus, que os fez ir ao cativeiro entre os pagãos; mas eu os reuni em sua própria terra, e não mais deixei nenhum deles lá.
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
29 Nem esconderei mais a minha face deles, porque eu derramei o meu Espírito sobre a casa de Israel, diz o Senhor DEUS.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 39, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.