Ezequiel 38

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
1 E a palavra do SENHOR veio a mim, dizendo:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
2 Filho do homem, posiciona a tua face contra Gogue, terra de Magogue, o principal príncipe de Meseque e Tubal, e profetiza contra ele,
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
3 e dize: Assim diz o Senhor DEUS: Eis que eu sou contra ti, ó Gogue, principal príncipe de Meseque e de Tubal;
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
4 E, eu te virarei de volta, e colocarei anzóis nas tuas mandíbulas, e te trarei adiante, e a todo o teu exército, cavalos e cavaleiros, todos eles vestidos com todos os tipos de armadura, uma grande companhia com broquéis e escudos, todos manejando espadas;
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
5 a Pérsia, a Etiópia e a Líbia com eles; todos eles com escudo e elmo;
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
6 Gômer e todas as suas tropas; a casa de Togarma, do extremo norte e todas as suas tropas, e muitas pessoas contigo.
7 “ ‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
7 Estejas tu preparado, e prepara-te a ti mesmo, tu e toda a tua companhia que está reunida para ti, e sê tu um guarda para eles.
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
8 Depois de muitos dias serás visitado; nos últimos anos tu virás à terra que é trazida de volta da espada, e é juntada dentre muitas pessoas, contra os montes de Israel, que sempre foram desertos; mas é gerada dentre as nações, e habitarão seguramente todos eles.
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
9 Tu subirás, e virás como uma tempestade, serás como uma nuvem para cobrir a terra, tu e todas as suas tropas, e muitas pessoas contigo.
10 “ ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
10 Assim diz o Senhor DEUS: E também virá a suceder, que ao mesmo tempo coisas virão à tua mente, e tu terás um mau pensamento,
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
11 e dirás: Subirei à terra de aldeias não muradas; eu irei àqueles que estão em repouso, que habitam seguramente; todos eles habitando sem muros, e não tendo barras nem portões,
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
12 para tomar o despojo, e tomar a presa; para virar a tua mão sobre os lugares assolados que estão agora habitados, e sobre o povo que está reunido dentre as nações, o qual adquiriu gado e bens, que habitam no meio da terra.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?” ’ ”
13 Sebá e Dedã, e os mercadores de Társis, todos os seus jovens leões te dirão: És tu vindo para tomar o despojo? Ajuntaste a tua companhia para tomar a presa? Para carregar a prata e o ouro, para tomar o gado e os bens, para levar um grande despojo?
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
14 Portanto, filho do homem, profetiza e dize a Gogue: Assim diz o Senhor DEUS: No dia em que meu povo de Israel habitar seguramente, tu não o saberás?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
15 E virás do teu lugar, das partes do norte, tu e muitas pessoas contigo, todos eles montados sobre cavalos, uma grande companhia, e um poderoso exército;
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
16 e tu subirás contra o meu povo Israel, como uma nuvem, para cobrir a terra. Isso será nos últimos dias, e hei de trazer-te contra a minha terra, para que os pagãos possam me conhecer, quando eu for santificado em ti, ó Gogue, diante dos seus olhos.
17 “ ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
17 Assim diz o Senhor DEUS: És tu aquele de quem eu falei nos tempos antigos, pelos meus servos, os profetas de Israel, os quais profetizaram naqueles dias muitos anos, que te traria contra eles?
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
18 E acontecerá no mesmo tempo quando Gogue vier contra a terra de Israel, diz o Senhor DEUS, que a minha fúria subirá à minha face.
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
19 Porque no meu ciúme, e no fogo da minha ira eu falei: Certamente, naquele dia haverá grande tremor na terra de Israel,
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
20 de tal modo que os peixes do mar, e as aves do céu, e os animais do campo, e todas as coisas rastejantes que rastejam sobre a terra, e todos os homens que estão sobre a face da terra tremerão à minha presença; e os montes serão derrubados, e os lugares íngremes cairão, e todo muro cairá ao chão.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
21 Porque eu chamarei uma espada contra ele através de todos os meus montes, diz o Senhor DEUS; a espada de cada homem será contra seu irmão.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
22 E contenderei contra ele com peste e com sangue; e choverei sobre ele, e sobre as suas tropas, e sobre as muitas pessoas que estão com ele, uma transbordante chuva e grandes pedras de granizo, fogo e enxofre.
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
23 Assim, eu me engrandecerei e me santificarei, e serei conhecido aos olhos de muitas nações; e eles saberão que eu sou o SENHOR.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 38, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.