Ezequiel 11

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
1 Além disso, o Espírito me levantou, e me trouxe à porta leste da casa do SENHOR, a qual olha em direção ao leste; e eis à porta do portão vinte e cinco homens, entre os quais eu vi a Jaazanias, filho de Azur, e a Pelatias, filho de Benaia, príncipes do povo.
2 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
2 Então, ele me disse: Filho do homem, estes são os homens que maquinam o mal, e dão perverso conselho nesta cidade;
3 Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
3 os quais dizem: Isso não está próximo; edifiquemos casas; esta cidade é o caldeirão, e sejamos a carne.
4 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
4 Portanto, profetiza contra eles; profetiza, ó filho do homem.
5 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
5 E o Espírito do SENHOR caiu sobre mim, e me disse: Fala: Assim diz o SENHOR: Assim haveis falado, ó casa de Israel, porque eu conheço as coisas que vêm à vossa mente, cada uma delas.
6 Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
6 Multiplicastes os vossos mortos nesta cidade, e enchestes as suas ruas de mortos.
7 “Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
7 Portanto, assim diz o Senhor DEUS: Vossos mortos, que vós deitastes no meio dela, esses são a carne, e esta cidade é o caldeirão; mas eu vos tirarei do meio dela.
8 Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
8 Temestes a espada, e eu trarei uma espada sobre vós, diz o Senhor DEUS.
9 Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
9 E eu vos trarei para fora de seu meio, e vos entregarei nas mãos de estranhos, e executarei os meus juízos entre vós.
10 Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
10 Caireis pela espada, e eu vos julgarei na fronteira de Israel; e sabereis que eu sou o SENHOR.
11 Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
11 Esta cidade não será o vosso caldeirão, nem vós sereis a carne no meio dela; mas eu vos julgarei na fronteira de Israel;
12 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
12 e vós sabereis que eu sou o SENHOR, porque não andastes nos meus estatutos, nem executastes os meus juízos, mas fizestes segundo as maneiras dos pagãos que estão ao redor de vós.
13 Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
13 E sucedeu, quando eu profetizava, que Pelatias, filho de Benaia, morreu. Então, eu caí sobre a minha face, e clamei com alta voz, e disse: Ah! Senhor DEUS! Darás tu um fim total aos remanescentes de Israel?
14 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
14 Novamente, a palavra do SENHOR veio a mim, dizendo:
15 “Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
15 Filho do homem, teus irmãos, até teus irmãos, os homens de teu parentesco, e toda a casa de Israel completamente, são aqueles a quem os habitantes de Jerusalém disseram: Apartai-vos para longe do SENHOR; a nós esta terra é dada em possessão.
16 “Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
16 Portanto, dize: Assim diz o Senhor DEUS: Embora eu os tenha lançado para longe entre os pagãos, e embora eu os tenha espalhado entre as nações, ainda assim, eu serei para eles como um pequeno santuário, nas regiões para onde eles virão.
17 “Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
17 Portanto, dize: Assim diz o Senhor DEUS: Hei de ajuntar-vos do meio do povo, e vos reunirei fora das nações onde fostes espalhados, e vos darei a terra de Israel.
18 “Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
18 E eles virão ali, e tirarão todas as suas coisas detestáveis dela e todas as suas abominações.
19 Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
19 E eu lhes darei um só coração, e colocarei um novo espírito dentro de vós; e tomarei o coração de pedra para fora da sua carne, e lhes darei um coração de carne;
20 Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
20 para que eles possam andar nos meus estatutos, e guardar as minhas ordenanças, e cumpri-las; e eles serão o meu povo, e eu serei o seu Deus.
21 Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
21 Mas, quanto àquele cujo coração andar segundo o coração das suas coisas detestáveis, e as suas abominações, eu recompensarei o seu caminho sobre suas próprias cabeças, diz o Senhor DEUS.
22 Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
22 Então, os querubins elevaram as suas asas, e as rodas do lado deles; e a glória do Deus de Israel estava sobre eles.
23 Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
23 E a glória do SENHOR subiu do meio da cidade; e ficou sobre o monte que está no lado leste da cidade.
24 Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn.
24 Em seguida, o Espírito me levantou, e me trouxe em visão pelo Espírito de Deus para dentro da Caldeia, para aqueles do cativeiro. Então, a visão que eu havia tido ascendeu de mim.
25 mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.
25 Então, eu falei àqueles do cativeiro todas as coisas que o SENHOR havia me mostrado.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ezequiel 11, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.