Ester 2
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Ahaswerusi ọba sì dáwọ́ ìbínú un rẹ̀ dúró, ó rántí i Faṣti àti ohun tí ó ti ṣe àti àṣẹ tí ó pa nípa tirẹ̀.
1 Depois destas coisas, quando a ira do rei Assuero foi aplacada, ele se lembrou de Vasti, e do que ela havia feito, e do que foi decretado contra ela.
2 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ ọba tí ó wà ní ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a wá ọmọbìnrin arẹwà tí kò ì ti mọ ọkùnrin rí fún ọba.
2 Então disseram os servos do rei que lhe ministravam: Busquem-se para o rei jovens virgens e formosas;
3 Àti pé kí ọba kí ó yan àwọn aláṣẹ ní gbogbo agbègbè ilẹ̀ ọba láti kó gbogbo àwọn arẹwà ọmọbìnrin wọ̀nyí jọ sí ilé àwọn obìnrin ní ilé ìṣọ́ Susa. Kí a kó wọn fún ìtọ́jú Hegai, ìwẹ̀fà ọba, ẹni tí ó ṣe olùtọ́jú àwọn obìnrin; kí a ṣe ìtọ́jú u wọn dáradára.
3 e que o rei designe em todas as províncias do seu reino oficiais, para que eles possam reunir todas as jovens virgens e formosas no palácio de Susã, na casa das mulheres, sob a custódia de Hegai, o camareiro do rei, guarda das mulheres; e que sejam entregues as suas coisas de purificação;
4 Nígbà náà kí ọmọbìnrin tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn kí ó jẹ́ ayaba dípò Faṣti.” Ìmọ̀ràn yìí tẹ́ ọba lọ́rùn, ó sì tẹ̀lé e.
4 e que a donzela que agradar ao rei seja rainha no lugar de Vasti. E isto agradou ao rei; e ele assim o fez.
5 Ó sì ṣe ní ìgbà náà ará a Júù kan wà ní ilé ìṣọ́ ti Susa, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mordekai ọmọ Jairi, ọmọ Ṣimei, ọmọ Kiṣi, ẹ̀yà Benjamini,
5 Ora, havia um certo judeu, no palácio de Susã, cujo nome era Mardoqueu, o filho de Jair, o filho de Simei, o filho de Quis, um benjamita;
6 ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti gbé lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu, lára àwọn tí wọ́n kó ní ìgbèkùn pẹ̀lú ọba Jekoniah ọba Juda.
6 que havia sido levado de Jerusalém com os cativos que haviam sido levados com Jeconias, o rei de Judá, os quais Nabucodonosor, o rei de Babilônia havia levado consigo.
7 Mordekai ní arákùnrin kan ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hadassa, ẹni tí ó tọ́ dàgbà nítorí tí kò ní baba bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní ìyá. Obìnrin yìí, ẹni tí a tún mọ̀ sí Esteri, ó dára ó sì lẹ́wà, Mordekai mú u gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ nígbà tí baba àti ìyá rẹ̀ ti kú.
7 E ele trouxe Hadassa, isto é, Ester, a filha do seu tio; pois ela não tinha nem pai nem mãe, e a criada era formosa e bela; e morrendo seu pai e sua mãe, Mardoqueu tomou por sua própria filha.
8 Nígbà tí a ti kéde òfin àti àṣẹ ọba, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọbìnrin ni a kó wá sí ilé ti ìṣọ́ Susa, sí abẹ́ ìtọ́jú Hegai. A sì mú Esteri náà wá sí ààfin ọba pẹ̀lú, a fà á lé Hegai lọ́wọ́, ẹni tí ó jẹ́ alábojútó ilé àwọn obìnrin.
8 Assim, sucedeu, quando o mandamento do rei e o seu decreto foi ouvido, e quando muitas donzelas reuniram-se no palácio de Susã, sob a custódia de Hegai, que Ester também foi trazida à casa do rei, à custódia de Hegai, o guarda das mulheres.
9 Ọmọbìnrin náà sì wù ú, ó sì rí ojúrere rẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó pèsè àwọn ohun tí ó dára àti oúnjẹ pàtàkì fún un. Ó sì yan àwọn ìránṣẹ́bìnrin wúńdíá méje láti ààfin ọba òun àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà lọ sí ibi tí ó dára jù nínú ilé àwọn obìnrin.
9 E a donzela o agradou, e ela obteve sua bondade; e ele prontamente deu a ela as coisas para a purificação, com as coisas que pertenciam a ela, como também em lhe dar sete moças de respeito da casa do rei; e a fez passar com as suas moças ao melhor lugar da casa das mulheres.
10 Esteri kò tí ì sọ nípa àwọn ènìyàn àti ìdílé e rẹ̀, nítorí Mordekai ti pàṣẹ fún un pé kí ó má ṣe sọ ọ́.
10 Ester não havia apresentado o seu povo, nem a sua parentela; porquanto Mardoqueu havia lhe ordenado de que ela não deveria apresentá-los.
11 Ní ojoojúmọ́ ni Mordekai máa ń rìn ní iwájú ilé àwọn obìnrin láti wo bí Esteri ṣe wà ní àlàáfíà àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.
11 E Mardoqueu andava todos os dias diante do átrio da casa das mulheres, para saber como Ester estava, e o que lhe sucederia.
12 Kí àkókò tó tó fún obìnrin kọ̀ọ̀kan láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Ahaswerusi, ó ní láti lo ohun èlò tí ń mú ara lẹ́wà tí a yàn fún àwọn obìnrin fún oṣù méjìlá, yóò lo òróró òjìá fún oṣù mẹ́fà, yóò sì lo ohun èlò olóòórùn dídùn tùràrí àti ìpara fún oṣù mẹ́fà pẹ̀lú.
12 Ora, quando chegou a hora de cada donzela adentrar ao rei Assuero, depois de ter estado por doze meses, segundo o costume das mulheres (pois assim eram os dias do cumprimento da sua purificação, a saber, seis meses com azeite de mirra, e seis meses com aromas doces, e com outras coisas para a purificação das mulheres);
13 Báyìí ni yóò ṣe lọ síwájú ọba: ohunkóhun tí ó bá béèrè ni wọ́n fi fún un láti inú ilé àwọn obìnrin lọ sí ààfin ọba.
13 então, assim veio cada donzela até o rei; tudo o que ela desejasse lhe era concedido, para levar consigo da casa das mulheres até a casa do rei.
14 Ní alẹ́ ni yóò lọ síbẹ̀, tí ó bá sì di òwúrọ̀ yóò padà sí ilé kejì nínú ilé àwọn obìnrin ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣaaṣigasi ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó máa ń ṣe ìtọ́jú àwọn àlè. Òun kò ní lọ sí ọ̀dọ̀ ọba mọ́ àyàfi tí inú ọba bá dùn sí i, tí ó sì ránṣẹ́ pé ó ní orúkọ obìnrin.
14 À tarde ela entrava, e pela manhã voltava para a segunda casa das mulheres, para a custódia de Saasgaz, o camareiro do rei, o qual guardava as concubinas; ela não adentrava mais a presença do rei, exceto se o rei se deleitasse nela, e se ela fosse chamada pelo nome.
15 Nígbà tí ó kan Esteri (ọmọbìnrin tí Mordekai gbà ṣe ọmọ, ọmọbìnrin arákùnrin rẹ̀ tí ó ń jẹ́ Abihaili) láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọn kò béèrè fún ohunkóhun ju èyí tí Hegai, ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó jẹ́ olùtọ́jú ilé àwọn obìnrin sọ pé kí ó ṣe lọ. Esteri sì rí ojúrere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn tí ó rí i.
15 Ora, quando chegou a vez de Ester, a filha de Abiail, o tio Mardoqueu, que lhe havia tomado por sua filha, veio para adentrar ao rei, ela não exigiu nada além daquilo que Hegai, o camareiro do rei, o guardador das mulheres, indicou. E Ester obteve favor à vista de todos os que cuidavam dela.
16 A mú Esteri lọ síwájú ọba Ahaswerusi ní ibùgbé ọba ní oṣù kẹwàá, tí ó jẹ́ oṣù Tebeti, ní ọdún keje ìjọba rẹ̀.
16 Assim, Ester foi levada até o rei Assuero, dentro da sua casa real no décimo mês, que é o mês de tebete, no sétimo ano do seu reinado.
17 Esteri sì wu ọba ju àwọn obìnrin tókù lọ, Ó sì rí ojúrere àti oore-ọ̀fẹ́ gbà ju ti àwọn wúńdíá tókù lọ. Nítorí náà ó fi adé ọba dé e ní orí ó sì fi ṣe ayaba dípò Faṣti.
17 E o rei amou Ester acima de todas as mulheres, e ela obteve graça e favor à sua vista mais do que todas as virgens; de modo que ele pôs sobre a sua cabeça a coroa real, e a fez rainha no lugar de Vasti.
18 Ọba sì ṣe àsè ńlá, àsè Esteri, fún gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì kéde ìsinmi jákèjádò ìgbèríko ó sì pín ẹ̀bùn fún wọn pẹ̀lú bí ọba ṣe lawọ́ tó.
18 Então, o rei fez um grande banquete para todos os príncipes e aos seus servos, a saber, o banquete de Ester; e ele deu alívio para as províncias, e deu presentes, de acordo com o estado do rei.
19 Nígbà tí àwọn wúńdíá tún péjọ ní ìgbà kejì, Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba.
19 E, quando as virgens se reuniram pela segunda vez, então Mardoqueu se assentou no portão do rei.
20 Ṣùgbọ́n Esteri pa àṣírí ìdílé e rẹ̀ àti ibi tí ó ti wá mọ́ gẹ́gẹ́ bí Mordekai ṣe sọ fún un pé kí ó ṣe, nítorí tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ tí Mordekai fún un gẹ́gẹ́ bí ó ṣe máa ń ṣe nígbà tí ó wà ní ọ̀dọ̀ Mordekai.
20 Ester ainda não tinha declarado a sua parentela, nem o seu povo, conforme Mardoqueu lhe havia ordenado; pois Ester cumpria o mandamento de Mardoqueu, como quando estava sendo criada por ele.
21 Ní àsìkò tí Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba, Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n máa ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, wọ́n bínú, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa ọba Ahaswerusi.
21 Naqueles dias, enquanto Mardoqueu se assentava no portão do rei, dois dos camareiros do rei, Bigtã e Teres, daqueles que guardavam a porta, ficaram irados, e procuraram lançar mão sobre o rei Assuero.
22 Ṣùgbọ́n Mordekai sì mọ̀ nípa ọ̀tẹ̀ náà, ó sọ̀ fún ayaba Esteri, Esteri sì sọ fún ọba, wọ́n sì fi ọlá fún Mordekai.
22 E isso veio ao conhecimento de Mardoqueu, que contou à rainha Ester; e Ester disse ao rei em nome de Mardoqueu.
23 Nígbà tí wọ́n sì wádìí ọ̀rọ̀ náà tí ó sì jásí òtítọ́, a sì so àwọn ìjòyè méjèèjì náà kọ́. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a kọ sínú ìwé ìtàn ní iwájú ọba.
23 E, quando foi feito inquérito sobre a questão, isto foi achado; por isso os dois foram pendurados em uma árvore; e isto foi escrito no livro das Crônicas diante do rei.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ester 2, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.