Ester 1
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Èyí ni ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ìgbà Ahaswerusi, tí ó jẹ ọba lórí ẹ̀tàdínláàdóje (127) ìletò bẹ̀rẹ̀ láti India títí ó fi dé Etiopia.
1 Ora, sucedeu nos dias de Assuero, (este é o Assuero que reinou da Índia até a Etiópia, sobre cento e vinte e sete províncias).
2 Ní àkókò ìgbà náà ọba Ahaswerusi ń ṣe ìjọba ní orí ìtẹ́ ẹ rẹ̀ ní ilé ìṣọ́ ti Susa,
2 Que naqueles dias, quando o rei Assuero assentou-se no trono do seu reino, o qual estava no palácio, em Susã,
3 ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ọlọ́lá àti ìjòyè. Àwọn olórí ológun láti Persia àti Media, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn ọlọ́lá ìletò wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
3 no terceiro ano do seu reinado, ele fez um banquete para todos os seus príncipes e seus servos; estando perante ele o poder da Pérsia e da Média, e os nobres e príncipes das províncias;
4 Ó ṣe àfihàn púpọ̀ ọrọ̀ ìjọba rẹ̀ àti dídán àti ògo ọláńlá rẹ̀ fún ọgọ́sàn-án ọjọ́ gbáko.
4 quando ele mostrou as riquezas do seu glorioso reino e a honra da sua excelente majestade, por muitos dias, a saber, cento e oitenta dias.
5 Nígbà tí ọjọ́ wọ̀nyí kọjá, ọba ṣe àsè fún ọjọ́ méje, nínú ọgbà tí ó wà nínú àgbàlá ààfin ọba, gbogbo ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni tí ó lọ́lá jùlọ, tí wọ́n wà ní ilé ìṣọ́ ti Susa.
5 E quando estes dias haviam expirado, o rei fez um banquete para todo o povo que estava presente no palácio de Susã, tanto para os grandes, como para os pequenos, sete dias, no átrio do jardim do palácio do rei;
6 Ọgbà náà ní aṣọ fèrèsé funfun àti aláwọ̀ òféfèé. Àwọn okùn tí a fi aṣọ aláwọ̀ funfun àti aláwọ̀ elése àlùkò rán ni a fi ta á mọ́ òrùka fàdákà lára àwọn òpó mabu. Àwọn ibùsùn tí a fi wúrà àti fàdákà ṣe wà níbi pèpéle òkúta tí a fi ń tẹ́lẹ̀ ilé tí ó jẹ́ mabu, píálì àti òkúta olówó iyebíye mìíràn.
6 e havia toldos brancos, verdes e azuis, presos por cordões de linho fino e de púrpura a argolas de prata e a colunas de mármore; os leitos eram de ouro e de prata, sobre um pavimento de mármore vermelho, e azul e branco, e mármore preto.
7 Kọ́ọ̀bù wúrà onídìí-odó ni a fi ń bu wáìnì fún wọn mu, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì yàtọ̀ sí èkejì, wáìnì ọba pọ̀ púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ọba ṣe lawọ́ sí.
7 E eles lhes deram de beber em vasos de ouro (sendo que os vasos eram diferentes uns dos outros) e vinho real em abundância, segundo o estado do rei.
8 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba a fi ààyè gba àlejò kọ̀ọ̀kan láti mu tó bí ó bá ti fẹ́, nítorí ọba ti pàṣẹ fún gbogbo àwọn ti ń bu wáìnì láti bù fún ẹnìkọ̀ọ̀kan bí wọ́n bá ṣe béèrè fún mọ.
8 E a bebida era de acordo com a lei; ninguém forçou; porque assim o rei tinha indicado a todos os oficiais da sua casa, para que fizessem conforme a vontade de cada homem.
9 Ayaba Faṣti náà ṣe àsè fún àwọn obìnrin ní ààfin ọba Ahaswerusi.
9 Além disso, a rainha Vasti fez um banquete para as mulheres na casa real que pertencia ao rei Assuero.
10 Ní ọjọ́ keje, nígbà tí wáìnì mú inú ọba dùn, ó pàṣẹ fún Mehumani, Bista, Harbona, Bigta àti Abagta, Setari àti Karkasi, àwọn ìwẹ̀fà méje tí ń jíṣẹ́ fún Ahaswerusi.
10 No sétimo dia, estando já o coração do rei alegre com o vinho, ele ordenou a Meumã, Bizta, Harbona, Bigtá, e Abagta, Zetar e a Carcas, os sete camareiros que serviam na presença do rei Assuero,
11 Kí wọn mú ayaba Faṣti wá síwájú rẹ̀, ti òun ti adé ọba rẹ̀, kí ó lè wá fi ẹwà rẹ̀ hàn àwọn ènìyàn àti àwọn ọlọ́lá, nítorí tí ó rẹwà.
11 para trazerem a rainha Vasti diante do rei, com a coroa real, para mostrar aos povos e aos príncipes a sua beleza; porque ela era formosa de se olhar.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ jẹ́ iṣẹ́ ọba, ayaba Faṣti kọ̀ láti wá. Nígbà náà ni ọba bínú gidigidi, ìbínú náà sì pọ̀ jọjọ.
12 A rainha Vasti, porém, recusou-se a vir diante do mandamento do rei por meio dos seus camareiros; pelo que o rei ficou muito irado, e ardeu nele a sua ira.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ ní ìgbà gbogbo, ọba máa ń béèrè ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ní ìmọ̀ òfin àti ìdájọ́, ó sọ ọ́ fún àwọn amòye tí wọ́n mòye àkókò,
13 Então, o rei disse aos sábios, os quais conheciam os tempos (porque assim era o costume do rei para com todos os que conheciam a lei e o juízo;
14 àwọn tí wọ́n súnmọ́ ọba àwọn wọ̀nyí ni Karṣina, Ṣetari, Admata, Tarṣiṣi, Meresi, Marsena àti Memukani, àwọn ọlọ́lá méje ti Persia àti Media tí wọ́n ṣe pàtàkì sí ọba, wọ́n sì tún wà ní ibi gíga ní ìjọba.
14 e os próximos a ele eram: Carsena, Setar, Admata, Társis, Meres, Marsena e Memucã, os sete príncipes da Pérsia e da Média, os quais viam a face do rei, e se assentavam por primeiro no reino):
15 Ó béèrè pé, “Kí ni a lè ṣe sí ayaba Faṣti gẹ́gẹ́ bí òfin? Nítorí kò tẹríba fún àṣẹ ọba Ahaswerusi tí àwọn ìwẹ̀fà ọba sọ fún un.”
15 O que faremos à rainha Vasti, de acordo com a lei, porque ela não cumpriu o mandamento do rei Assuero por intermédio dos camareiros?
16 Memukani sì dáhùn níwájú ọba àti àwọn ọlọ́lá pé, “Ayaba Faṣti ti ṣe búburú, kì í ṣe sí ọba nìkan ṣùgbọ́n sí gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní gbogbo agbègbè ilẹ̀ ọba Ahaswerusi.
16 E Memucã respondeu diante do rei e dos príncipes: A rainha Vasti não somente fez errado ao rei, mas também a todos os príncipes, e a todos os povos que há em todas as províncias do rei Assuero.
17 Nítorí ìwà ayaba yìí yóò tàn dé ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn obìnrin, tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ wọn yóò di gígàn lójú u wọn, wọn yóò sì sọ pé, ọba Ahaswerusi pàṣẹ pé kí á mú ayaba Faṣti wá síwájú òun, ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti wá.
17 Porque este ato da rainha tornar-se-á conhecido a todas as mulheres, de modo que elas desprezarão os seus maridos aos seus olhos, quando isto for relatado: O rei Assuero ordenou que a rainha Vasti fosse trazida diante dele, mas ela não veio.
18 Ní ọjọ́ yìí gan an ni àwọn ọlọ́lá obìnrin Persia àti ti Media tí wọ́n ti gbọ́ nípa ìwà ayaba wọn yóò ṣe bẹ́ẹ̀ sí gbogbo àwọn ìjòyè ọba bákan náà. Àfojúdi àti àìnírẹ́pọ̀ tí kò lópin yóò wà.
18 Neste dia, igualmente as senhoras da Pérsia e da Média, que ouviram o ato da rainha, dirão a todos os príncipes dos reis. Assim suscitar-se-á muitíssima contenda e ira.
19 “Nítorí náà, bí ó bá tọ́ lójú ọba, jẹ́ kí ó gbé àṣẹ ọba jáde, kí ó sì jẹ́ kí ó wà ní àkọsílẹ̀ pẹ̀lú òfin Persia àti Media, èyí tí kò le é parẹ́, pé kí Faṣti kí ó má ṣe wá síwájú ọba Ahaswerusi. Kí ọba sì fi oyè ayaba rẹ̀ fún ẹlòmíràn tí ó sàn jù ú lọ.
19 Se for do agrado do rei, saia da sua parte um mandamento real, e escreva-se entre as leis dos persas e dos medos, para que não seja revogado, que Vasti não venha mais diante do rei Assuero; e que o rei dê a sua propriedade real para outra que seja melhor do que ela.
20 Nígbà náà tí a bá kéde òfin tí ọba ṣe ká gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin ni yóò bọ̀wọ̀ fún ọkọ wọn, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó kéré títí dé ọ̀dọ̀ ẹni ńlá.”
20 E quando o decreto que o rei fizer, for publicado por todo o seu império (porquanto este é grande) todas as esposas darão aos seus maridos honra, tanto ao grande, como ao pequeno.
21 Ìmọ̀ràn yìí sì tẹ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ lọ́rùn, nítorí náà ọba ṣe gẹ́gẹ́ bí Memukani ṣé sọ.
21 E o dizer agradou ao rei e aos príncipes; e o rei fez conforme a palavra de Memucã;
22 Ó kọ̀wé ránṣẹ́ sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ ọba rẹ̀, ó kọ̀wé sí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé, ó kọ̀wé sí àwọn ènìyàn kọ̀ọ̀kan ní èdè wọn, Ó tẹnumọ́ ní èdè oníkálùkù pé kí olúkúlùkù ọkùnrin máa ṣàkóso ilé rẹ̀.
22 porque ele enviou cartas a todas as províncias do rei, a cada província segundo a sua escrita, e a cada povo segundo a sua língua, para que todo homem assumisse o comando da sua própria casa, e para que isto fosse publicado de acordo com a língua de cada povo.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Ester 1, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.