Esdras 7

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
1 Ora, depois destas coisas, no reinado de Artaxerxes, rei da Pérsia, Esdras, o filho de Seraías, o filho de Azarias, o filho de Hilquias,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
2 o filho de Salum, o filho de Zadoque, o filho de Aitube,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
3 o filho de Amarias, o filho de Azarias, o filho de Meraiote,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
4 o filho de Zeraías, o filho de Uzi, o filho de Buqui,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
5 o filho de Abisua, o filho de Fineias, o filho de Eleazar, o filho de Arão, o sumo sacerdote;
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
6 este Esdras subiu de Babilônia; e ele era um escriba hábil na lei de Moisés, dada pelo ­SENHOR Deus de Israel; de acordo com a mão do ­SENHOR, o seu Deus, que estava sobre ele, e o rei lhe deu tudo quanto lhe pedira.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
7 No sétimo ano do rei Artaxerxes subiram para Jerusalém alguns dos filhos de Israel, e dos sacerdotes, e dos levitas, e dos cantores, e dos porteiros e dos Netineus.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
8 E ele veio para Jerusalém no quinto mês, o qual era o sétimo ano do rei.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
9 Pois no primeiro dia do primeiro mês ele partiu de Babilônia, e no primeiro dia do quinto mês chegou a Jerusalém, de acordo com a boa mão do seu Deus sobre ele.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
10 Porque Esdras havia preparado o seu coração para buscar a lei do ­SENHOR, e para executá-la, e para ensinar em Israel estatutos e juízos.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
11 Ora, esta é a cópia da carta que o rei Artaxerxes deu ao sacerdote Esdras, o escriba, a saber um escriba das palavras dos mandamentos do ­SENHOR, e dos seus estatutos para Israel.
12 Artasasta, ọba àwọn ọba.
12 Artaxerxes, rei dos reis, ao sacerdote Esdras, um escriba da lei do Deus do céu, perfeita paz, e em tal tempo.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
13 Eu faço um decreto, para que todos do povo de Israel, e dos seus sacerdotes e levitas, no meu reino, que estejam dispostos para ir a Jerusalém, de sua livre vontade, que vá contigo.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
14 Porquanto como tu és enviado do rei, e dos seus sete conselheiros, para investigar acerca de Judá e de Jerusalém, de acordo com a lei do teu Deus que está na tua mão;
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
15 e para carregar a prata e ouro, a qual o rei e os seus conselheiros têm oferecido livremente ao Deus de Israel, cuja habitação está em ­Jerusalém,
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
16 e toda a prata e ouro que puderes encontrar em todas as províncias de Babilônia, com a oferta voluntária do povo, e dos sacerdotes, ofertando deliberadamente para a casa do seu Deus que está em Jerusalém;
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
17 para que tu possas comprar, rapidamente, com este dinheiro novilhos, carneiros, cordeiros, com as suas ofertas de carne e as suas ofertas de bebida, e oferecê-los sobre o altar da casa do vosso Deus que está em Jerusalém.
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
18 Fazei com o restante da prata e do ouro tudo o que parecer bom a ti e a teus irmãos, o fareis conforme a vontade do vosso Deus.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
19 Também os vasos que te são dados para o serviço da casa do teu Deus, entrega-os diante do Deus de Jerusalém.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
20 E tudo o mais que for necessário para a casa do teu Deus, o que te for preciso dar, dá-lo-ás da casa dos tesouros do rei.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
21 Eu, sim eu, o rei Artaxerxes, faço um decreto a todos os tesoureiros que estão além do rio, que se entregue prontamente tudo o que vos pedir o sacerdote Esdras, o escriba da lei do Deus do céu,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
22 até uma centena de talentos, e até uma centena de medidas de trigo, e até uma centena de batos de vinho, e até uma centena de batos de azeite, e sal sem prescrever quanto.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
23 Tudo o quanto for ordenado pelo Deus do céu, seja isto diligentemente feito para a casa do Deus do céu; porquanto por que deveria haver ira contra o domínio do rei e dos seus filhos?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
24 Nós também, certificamo-vos que, no tocante a qualquer um dos sacerdotes e levitas, cantores, porteiros, netineus, ou ministros desta casa de Deus, não será lícito impor portagem, tributo, ou taxas alfandegárias sobre eles.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
25 E tu, Esdras, segundo a sabedoria do teu Deus, que está na tua mão, estabelece magistrados e juízes, os quais possam julgar todos os povos que estão além do rio, todos os tais que conheçam as leis do teu Deus; e ensinai aqueles que não as conhecem.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
26 E todo aquele que não quiser executar a lei do teu Deus, e a lei do rei, seja o juízo executado prontamente sobre ele, seja ele para a morte, ou para o banimento, ou para o confisco de bens, ou para o aprisionamento.
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
27 Bendito seja o ­SENHOR Deus dos nossos pais, que tem posto tal coisa como esta no coração do rei, para embelezar a casa do ­SENHOR a qual está em Jerusalém;
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
28 e tem estendido misericórdia a mim diante do rei, e dos seus conselheiros, e diante de todos os príncipes poderosos do rei. E eu fui fortalecido à medida que a mão do ­SENHOR meu Deus esteve sobre mim, e eu reuni de Israel chefes para subirem comigo.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Esdras 7, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.