Esdras 6

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
1 Então o rei Dario, editou um decreto, e uma investigação foi feita na casa dos rolos, onde os tesouros eram depositados em Babilônia.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀.
2 E foi encontrado, em Acmetá, no palácio que está na província dos medos, um rolo, e nele estava um registro escrito assim:
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.
3 No primeiro ano do rei Ciro, o próprio rei Ciro fez um decreto acerca da casa de Deus em Jerusalém: Que a casa seja edificada, o lugar onde eles ofereciam sacrifícios, e que os seus fundamentos sejam fortemente lançados; a sua altura de sessenta côvados, e a sua largura de sessenta côvados;
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
4 com três fileiras de grandes pedras, e uma fileira de madeira nova; e que as despesas sejam dadas a partir da casa do rei;
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
5 e também que sejam restaurados os vasos de ouro e de prata da casa de Deus, os quais Nabucodonosor retirou do templo que está em Jerusalém, e os trouxe para Babilônia, e voltem novamente para o templo que está em Jerusalém, cada um ao seu lugar, e ponde-os na casa de Deus.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
6 Agora, portanto, Tatenai, governador dalém do rio, Setar-Bozenai, e os vossos companheiros, os afarsaquitas, os quais estão além do rio, estejais vós longe dali;
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
7 deixai a obra desta casa de Deus; que o governador dos judeus e os anciãos dos judeus edifiquem esta casa de Deus no seu lugar.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí.
8 Além disso, eu faço um decreto do que vós fareis aos anciãos daqueles judeus para a edificação desta casa de Deus; para que dos bens do rei, a saber, do tributo dalém do rio, as despesas sejam dadas imediatamente a estes homens, para que eles não sejam prejudicados.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
9 E aquilo do que eles necessitarem, tanto os novilhos novos, quanto carneiros e cordeiros, para as ofertas queimadas do Deus do céu; trigo, sal, vinho e azeite, segundo a indicação dos sacerdotes que estão em Jerusalém, que lhes seja dado, dia após dia, sem falta;
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
10 e para que eles possam oferecer sacrifícios de cheiro suave ao Deus do céu, e orar pela vida do rei, e dos seus filhos.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
11 Além disso, eu fiz um decreto, que qualquer um que alterar esta palavra, arranque-se uma estaca da sua casa, e sendo erguida, que ele seja pregado nela; e que a sua casa seja feita uma pilha de estrume por causa disso.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run.
12 E o Deus que fez habitar ali o seu nome, destrua todos os reis e povos que estenderem a sua mão para alterar e para destruir esta casa de Deus, a qual está em Jerusalém. Eu, Dario, fiz um decreto; que isto seja feito rapidamente.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
13 Então, Tatenai, governador deste lado do rio, Setar-Bozenai, e os seus companheiros, de acordo com aquilo que Dario, o rei, havia enviado, assim fizeram rapidamente.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
14 E os anciãos dos judeus edificaram, e prosperaram devido à profecia do profeta Ageu, e Zacarias, o filho de Ido. E eles edificaram, e a acabaram, de acordo com o mandamento do Deus de Israel, e de acordo com o mandamento de Ciro, e de Dario, e de Artaxerxes, rei da Pérsia.
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
15 E essa casa foi terminada no terceiro dia do mês de Adar, no sexto ano do reinado do rei Dario.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
16 E os filhos de Israel, os sacerdotes, e os levitas, e o restante dos filhos do cativeiro, celebraram com alegria a dedicação desta casa de Deus.
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó (400) akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 E ofereceram, na dedicação desta casa de Deus, uma centena de novilhos, duas centenas de carneiros, quatro centenas de cordeiros; e como oferta pelo pecado por todo o Israel, doze bodes, de acordo com o número das tribos de Israel.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
18 E eles puseram os sacerdotes nas suas divisões, e os levitas nas suas turmas, para o serviço de Deus, o qual está em Jerusalém; como está escrito no livro de Moisés.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
19 E os filhos do cativeiro celebraram a Páscoa no décimo quarto dia do primeiro mês.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
20 Porquanto os sacerdotes e os levitas foram purificados juntos, todos eles estavam puros, e mataram o cordeiro pascal para todos os filhos do cativeiro, e para os seus irmãos, os sacerdotes, e para si mesmos.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
21 Assim comeram, os filhos de Israel que tinham retornado do cativeiro, com todos os que com eles se separaram da imundície dos pagãos da terra, para buscarem o ­SENHOR Deus de Israel;
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
22 e celebraram a festa do pão ázimo sete dias com alegria; porque o ­SENHOR os tinha alegrado, tocando o coração do rei da Assíria a favor deles, para lhes fortalecer as suas mãos na obra da casa de Deus, o Deus de Israel.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Esdras 6, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.