Esdras 10

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
1 Ora, quando Esdras orou e quando ele confessou chorando e lançando-se ao chão diante da casa de Deus, ajuntou-se ali com ele uma mui grande congregação de homens e mulheres e crianças de Israel; porque o povo chorava mui amargamente.
2 Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
2 E Secanias, o filho de Jeiel, um dos filhos de Elão, disse a Esdras: Temos transgredido contra o nosso Deus, e temos tomado esposas estranhas do povo da terra; todavia agora há esperança em Israel acerca desta coisa.
3 Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
3 Agora, portanto, façamos um pacto com o nosso Deus para despedirmos todas as esposas, e os que delas são nascidos, de acordo com o conselho do meu senhor, e daqueles que tremem diante do mandamento do nosso Deus; e faça-se segundo a lei.
4 Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
4 Levanta-te; pois a ti pertence esta questão; nós também estaremos contigo; sê de boa coragem, e faze-o.
5 Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
5 Então, levantou-se Esdras, e ajuramentou os sumos sacerdotes, os levitas e todo o Israel, de que eles fariam de acordo com esta palavra. E eles juraram.
6 Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
6 Então, Esdras se levantou de diante da casa de Deus, e adentrou a câmara de Joanã, o filho de Eliasibe; e quando chegou ali, ele não comeu pão, nem bebeu água; porque se lamentava por causa da transgressão daqueles que haviam sido levados.
7 Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
7 E eles fizeram proclamação por todo o Judá e em Jerusalém, a todos os filhos do cativeiro, para que todos eles se reunissem em Jerusalém;
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
8 e que todo aquele que não viesse dentro de três dias, de acordo com o conselho dos príncipes e dos anciãos, todos os seus bens deveriam ser confiscados, e ele seria separado da congregação daqueles que tinham sido levados.
9 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
9 Então, todos os homens de Judá e de Benjamim se reuniram em Jerusalém dentro de três dias. Era o nono mês, no vigésimo dia do mês; e todo o povo assentava-se na rua da casa de Deus, tremendo por causa desta questão, e por causa da grande chuva.
10 Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
10 E o sacerdote Esdras pôs-se em pé, e disse-lhes: Vós tendes transgredido, e tendes tomado esposas estrangeiras, aumentando a transgressão de Israel.
11 Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
11 Agora, portanto, fazei confissão ao ­SENHOR Deus dos vossos pais, e fazei a sua vontade; e separai-vos dos povos da terra, e das esposas estrangeiras.
12 Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
12 Então toda a congregação respondeu e disse em voz alta: Como disseste, assim nós devemos fazer.
13 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
13 Porém, o povo é muito, e é um tempo de muita chuva, e não conseguimos ficar de pé na parte de fora, nem é isto uma obra de um dia ou dois; porque somos muitos que temos transgredido nesta questão.
14 Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
14 Que, agora, levantem-se os nossos governantes de todas as congregações, e que todos os que têm tomado esposas estrangeiras em nossas cidades venham em tempos estabelecidos, e com eles os anciãos de toda cidade, e os seus juízes, até que seja desviada de nós a ira ardente do nosso Deus por esta questão.
15 Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
15 Somente Jônatas, o filho de Asael, e Jazeías, o filho de Ticva, foram empregados nesta questão; e Mesulão e Sabetai, o levita, os ajudaram.
16 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
16 E assim fizeram os filhos do cativeiro. E Esdras, o sacerdote, com alguns chefes dos pais, segundo a casa dos seus pais, e todos eles pelos seus nomes, foram separados, e se assentaram no primeiro dia do décimo mês para examinar a questão.
17 ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
17 E eles concluíram com todos os homens que haviam tomado esposas estrangeiras no primeiro dia do primeiro mês.
18 Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
18 E entre os filhos dos sacerdotes foram achados quem tinha tomado esposas estrangeiras, a saber; dos filhos de Jesuá, o filho de Jozadaque, e os seus irmãos, Maaseias, e Eliézer, e Jaribe, e Gedalias.
19 Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
19 E deram-se as mãos, prometendo que despediriam as suas esposas; e sendo culpados, eles ofereceram um carneiro do rebanho pela sua transgressão.
20 Nínú ìran Immeri:
20 E dos filhos de Imer: Hanani e Zebadias.
21 Nínú ìran Harimu:
21 E dos filhos de Harim: Maaseias, e Elias, e Semaías, e Jeiel, e Uzias.
22 Nínú ìran Paṣuri:
22 E dos filhos de Pasur: Elioenai, Maaseias, Ismael, Nataneel, Jozabade e Elasa.
23 Lára àwọn ọmọ Lefi:
23 Também dos levitas: Jozabade, e Simei, e Quelaías (este é Quelita), e Petaías, Judá, e Eliézer.
24 Nínú àwọn akọrin:
24 Também dos cantores: Eliasibe; e dos porteiros: Salum, e Telém, e Uri.
25 Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù.
25 Além disso, de Israel, dos filhos de Parós: Ramias, e Jezias, e Malquias, e Miamim, e Eleazar, e Malquias, e Benaia.
26 Nínú ìran Elamu:
26 E dos filhos de Elão: Matanias, e Zacarias, e Jeiel, e Abdi, e Jeremote, e Elias.
27 Nínú àwọn ìran Sattu:
27 E dos filhos de Zatu: Elioenai, Eliasibe, Matanias, e Jeremote, e Zabade, e Aziza.
28 Nínú àwọn ìran Bebai:
28 E também dos filhos de Bebai: Joanã, Hananias, Zabai e Atlai.
29 Nínú àwọn ìran Bani:
29 E dos filhos de Bani: Mesulão, Maluque, e Adaías, Jasube, e Seal, e Jeremote.
30 Nínú àwọn Pahati-Moabu:
30 E dos filhos de Paate-Moabe: Adna, e Quelal, Benaia, Maaseias, e Matanias, e Bezalel, e Binui, e Manassés.
31 Nínú àwọn ìran Harimu:
31 E dos filhos de Harim: Eliézer, Issias, Malquias, Semaías, Simeão,
32 Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
32 Benjamim, Maluque e Semarias.
33 Nínú àwọn ìran Haṣumu:
33 Dos filhos de Hasum: Matenai, Matatá, Zabade, Elifelete, Jeremai, Manassés e Simei.
34 Nínú àwọn ìran Bani:
34 Dos filhos de Bani: Maadai, Anrão, e Uel,
35 Benaiah, Bediah, Keluhi
35 Benaia, Bedias, Queluí,
36 Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
36 Vanias, Meremote, Eliasibe,
37 Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
37 Matanias, Matenai, e Jaasai,
38 Àti Bani, àti Binnui:
38 e Bani, e Binui, Simei,
39 Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
39 e Selemias, e Natã, e Adaías,
40 Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
40 Macnadebai, Sasai, Sarai,
41 Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
41 Azarel, e Selemias, Semarias,
42 Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
42 Salum, Amarias e José.
43 Nínú àwọn ìran Nebo:
43 Dos filhos de Nebo: Jeiel, Matitias, Zabade, Zebina, Jadai, e Joel, ­Benaia.
44 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.
44 Todos estes haviam tomado esposas estrangeiras; e alguns deles tinham esposa de quem tiveram ­filhos.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Esdras 10, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.