Deuteronômio 20
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
1 Quando saíres à batalha contra os teus inimigos, e vires cavalos, e carruagens, e um povo maior que tu, não os temas; porque está contigo o SENHOR teu Deus, que te tirou da terra do Egito.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
2 E acontecerá que, quando te aproximares da batalha, que o sacerdote se chegará e falará ao povo,
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
3 e lhes dirá: Ouve, ó Israel, chegais neste dia à batalha contra os vossos inimigos; não fraquejem os vossos corações, não temais, e não tremais, nem vos aterrorizeis por causa deles;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
4 porque o SENHOR teu Deus é aquele que vai convosco, para pelejar por vós contra os vossos inimigos, para vos salvar.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
5 E os oficiais falarão ao povo, dizendo: Que homem existe que edificou uma nova casa, e não a consagrou? Que vá e volte à sua casa, para que não morra na batalha, e outro homem a consagre.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
6 E que homem é aquele que plantou uma vinha e ainda não comeu dela? Que também vá e volte à sua casa, para que não morra na batalha, e outro homem a coma.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
7 E que homem existe que desposou uma mulher e ainda não a recebeu? Que vá e volte à sua casa, para que não morra na batalha, e outro homem a receba.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
8 E os oficiais falarão mais ao povo, e dirão: Que homem existe que é temeroso e covarde? Que vá e volte à sua casa, para que o coração de seus irmãos não desfaleça, como o seu próprio coração.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
9 E acontecerá que, quando os oficiais tiverem terminado de falar ao povo, que nomearão capitães dos exércitos para liderar o povo.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
10 Quando chegares a uma cidade para pelejar contra ela, então proclamar-lhe-ás a paz.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
11 E acontecerá que, se ela te der uma resposta de paz, e te abrir as portas, todos os seus habitantes te servirão em trabalhos forçados.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
12 E se ela não fizer a paz contigo, mas guerrear contra ti, então a sitiarás,
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
13 e quando o SENHOR teu Deus a tiver entregado em tuas mãos, ferirás cada homem dali com o fio da espada;
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
14 mas as mulheres e os pequenos, e o gado, e tudo o que existe na cidade, e até todos os seus despojos, tomarás para ti; e comerás os despojos dos teus inimigos, que o SENHOR teu Deus te deu.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
15 Assim farás a todas as cidades que estiverem muito longe de ti, e que não forem das cidades dessas nações.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
16 Mas das cidades desses povos, que o SENHOR teu Deus te der como herança, não deixarás com vida nada que respire;
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
17 mas as destruirás completamente; isto é, os heteus, e os amorreus, os cananeus, e os ferezeus, os heveus e os jebuseus; como o SENHOR teu Deus te ordenou;
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
18 para que não te ensinem conforme as suas abominações que fizeram aos seus deuses; e para que não pequeis contra o SENHOR vosso Deus.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
19 Quando sitiares uma cidade por muito tempo, guerreando contra ela, para tomá-la, não destruirás as suas árvores, forçando nelas um machado, pois delas comerá, e não as derrubará (porque a árvore do campo é a vida do homem) para usá-las no cerco.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
20 Somente as árvores que souberes que não são árvores de alimentos, destruirás e cortarás; e edificarás baluartes contra a cidade que guerrear contra ti, até que seja conquistada.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar Deuteronômio 20, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.