2 Samuel 5
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
1 Então, vieram todas as tribos de Israel até Davi em Hebrom, e falaram, dizendo: Eis que somos o teu osso e a tua carne.
2 Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’ ”
2 Também em tempos passados, quando Saul era rei sobre nós, tu eras aquele que saías e entravas em Israel; e o SENHOR te disse: Tu alimentarás Israel, meu povo, e tu serás um capitão sobre Israel.
3 Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
3 Assim, todos os anciãos de Israel vinham até o rei em Hebrom; e o rei Davi fez um pacto com eles em Hebrom diante do SENHOR; e eles ungiram Davi rei sobre Israel.
4 Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
4 Davi tinha trinta anos de idade quando começou a reinar, e reinou por quarenta anos.
5 Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
5 Em Hebrom ele reinou sobre Judá sete anos e seis meses; e em Jerusalém reinou trinta e três anos sobre todo o Israel e Judá.
6 Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
6 E o rei e os seus homens foram para Jerusalém até os jebuseus, os habitantes da terra; que falaram a Davi, dizendo: Exceto se removeres os cegos e os aleijados, não entrarás aqui, querendo dizer, Davi não pode entrar aqui.
7 Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
7 Todavia, Davi tomou a fortaleza de Sião; que é a cidade de Davi.
8 Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
8 E Davi disse naquele dia: Todo aquele que subir pelo canal, e ferir os jebuseus, e os aleijados e os cegos, que são odiados pela alma de Davi, será chefe e capitão. Pelo que disseram: Os cegos e os aleijados não entrarão na casa.
9 Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
9 Assim, Davi habitou no forte, e o chamou de cidade de Davi. E Davi edificou o entorno desde Milo em direção ao interior.
10 Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 E Davi prosseguiu, e tornou-se grande, e o SENHOR Deus dos Exércitos estava com ele.
11 Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
11 E Hirão, rei de Tiro, enviou mensageiros a Davi, e árvores de cedro, e carpinteiros e pedreiros; e eles edificaram uma casa para Davi.
12 Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
12 E Davi percebeu que o SENHOR o havia estabelecido rei sobre Israel, e que ele havia exaltado o seu reino por causa de Israel, seu povo.
13 Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
13 E Davi tomou para si mais concubinas e mulheres de Jerusalém, depois de chegar de Hebrom; e houve ainda filhos e filhas nascidos a Davi.
14 Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
14 E estes são os nomes daqueles que lhe nasceram em Jerusalém; Samua, e Sobabe, e Natã, e Salomão,
15 Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
15 Ibar também, e Elisua, e Nefegue, e Jafia,
16 Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
16 e Elisama, e Eliada, e Elifelete.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
17 Todavia, quando os filisteus ouviram que eles haviam ungido Davi rei sobre Israel, todos os filisteus subiram em busca de Davi; e Davi ouviu isto, e desceu à fortaleza.
18 Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
18 Os filisteus também vieram e se espalharam no vale dos Refains.
19 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?”
19 E Davi consultou o SENHOR, dizendo: Subirei até os filisteus? Entregá-los-ás em minha mão? E o SENHOR disse a Davi: Sobe; pois, sem dúvida, entregarei os filisteus na tua mão.
20 Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
20 E Davi veio até Baal-Perazim, e Davi os feriu ali e disse: O SENHOR irrompeu sobre os meus inimigos diante de mim, tal como a brecha de águas. Por isso ele chamou o nome daquele lugar Baal-Perazim.
21 Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
21 E ali eles deixaram as suas imagens, e Davi e os seus homens as queimaram.
22 Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
22 E os filisteus subiram novamente, e se espalharam no vale dos Refains.
23 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
23 E quando Davi consultou o SENHOR, ele disse: Tu não subirás; mas faz um cerco por trás deles, e investe sobre eles contra as amoreiras.
24 Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
24 E será que, quando ouvires o som de um mover sobre a copa das amoreiras, então te moverás, porquanto então o SENHOR sairá adiante de ti, para ferir o exército dos filisteus.
25 Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.
25 E Davi assim o fez, como o SENHOR lhe havia ordenado; e feriu os filisteus desde Geba até chegar a Gezer.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Samuel 5, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.