2 Samuel 20

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé,
1 E ocorreu de haver ali um homem de Belial, cujo nome era Seba, o filho de Bicri, um benjamita; e ele soprou uma trombeta, e disse: Não temos parte alguma em Davi, tampouco temos herança no filho de Jessé: cada homem para a sua tenda, ó Israel.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
2 Assim, todos os homens de Israel deixaram de seguir Davi, e seguiram Seba, o filho de Bicri; porém, os homens de Judá se apegaram ao seu rei, desde o Jordão até Jerusalém.
3 Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
3 E Davi chegou à sua casa em Jerusalém; e o rei tomou as dez mulheres, as suas concubinas, as quais ele havia deixado para cuidar da casa, e as pôs sob guarda, e as alimentou, mas não entrou a elas. Assim, elas ficaram trancadas até o dia da sua morte, vivendo em viuvez.
4 Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
4 Então, o rei disse a Amasa: Reúne-me os homens de Judá dentro de três dias, e estejas tu aqui presente.
5 Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
5 Assim, Amasa foi reunir os homens de Judá; porém, ele tardou além da hora marcada que ele lhe havia indicado.
6 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
6 E Davi disse a Abisai: Agora Seba, o filho de Bicri, far-nos-á mais mal do que nos fez Absalão; toma tu os servos do teu senhor e persegue-o, para que ele não conquiste para si cidades fortificadas e escape de nós.
7 Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
7 E ali saíram atrás dele os homens de Joabe, e os quereteus, e os peleteus, e todos os valentes; e eles saíram de Jerusalém, para perseguir Seba, o filho de Bicri.
8 Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
8 Quando eles estavam junto à pedra grande que fica em Gibeão, Amasa foi adiante deles. E as vestes de Joabe, que ele havia posto, estavam nele cingidas; e sobre ela um cinto com uma espada presa sobre o seu lombo, na sua bainha, e enquanto ele avançava, ela caiu.
9 Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
9 E Joabe disse a Amasa: Estás tu com saúde, meu irmão? E Joabe pegou Amasa pela barba com a mão direita para beijá-lo.
10 Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
10 Porém, Amasa não prestou atenção à espada que estava na mão de Joabe; assim ele o feriu com ela na quinta costela, e derramou as suas entranhas no chão, e não voltou a atingi-lo; e ele morreu. Assim, Joabe e Abisai, o seu irmão, perseguiram Seba, o filho de Bicri.
11 Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
11 E um dos homens de Joabe pôs-se de pé ao seu lado, e disse: Aquele que favorecer Joabe, e aquele que for por Davi, que siga Joabe.
12 Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
12 E Amasa chafurdava-se no sangue, no meio do caminho principal. E quando o homem viu que todo o povo permanecia imóvel, ele removeu Amasa do caminho principal para o campo, e lançou um pano sobre ele, quando viu que todos os que se aproximavam dele ficavam imóveis.
13 Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
13 Quando ele foi removido do caminho principal, todo o povo continuou atrás de Joabe, para perseguir Seba, o filho de Bicri.
14 Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
14 E ele foi por todas as tribos de Israel até Abel, e até Bete-Maaca, e todos os beritas; e eles foram reunidos, e também foram atrás dele.
15 Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
15 E eles chegaram e o sitiaram em Abel de Bete-Maaca, e eles ergueram um aterro encostado à cidade, e este ficava dentro de uma trincheira; e todo o povo que estava com Joabe golpeou a muralha, para lançá-la abaixo.
16 Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’ ”
16 Então uma mulher sábia gritou da cidade: Ouvi, ouvi; dizei, rogo-vos, a Joabe: Vem aqui mais perto, para que eu possa falar contigo.
17 Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?”
17 E quando ele se aproximou dela, a mulher disse: És tu Joabe? E ele respondeu: Eu Sou Ele. Então, ela disse a ele: Ouve as palavras de tua criada. E ele respondeu: Estou ouvindo.
18 Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
18 Então ela falou, dizendo: Eles estavam acostumados a falar em tempos antigos, dizendo: Eles certamente pedirão conselho a Abel; e assim eles encerravam a questão.
19 Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
19 Sou eu uma das pacíficas e das fiéis em Israel; tu buscas destruir uma cidade e uma mãe em Israel; por que queres engolir a herança do SENHOR?
20 Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
20 E Joabe respondeu, e disse: Longe esteja isto, longe esteja de mim engolir ou destruir.
21 Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.”
21 A questão não é assim; mas um homem do monte Efraim, Seba, filho de Bicri por nome, levantou a sua mão contra o rei, contra o próprio Davi; entrega-mo somente, e partirei da cidade. E a mulher disse a Joabe: Eis que a sua cabeça te será lançada por sobre a muralha.
22 Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
22 Então a mulher foi a todo o povo em sua sabedoria; e eles cortaram a cabeça de Seba, o filho de Bicri, e a lançaram para Joabe. E ele soprou uma trombeta, e eles se retiraram da cidade, cada homem para a sua tenda. E Joabe retornou a Jerusalém, para o rei.
23 Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli;
23 Ora, Joabe estava sobre todo o exército de Israel; e Benaia, o filho de Joiada, estava sobre os quereteus e sobre os peleteus;
24 Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde;
24 e Adorão estava sobre o tributo; e Josafá, o filho de Ailude era o escrivão;
25 Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé;
25 e Seva era escriba; e Zadoque e Abiatar eram os sacerdotes;
26 Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.
26 e também Ira, o jairita, era o governador-mor junto a Davi.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Samuel 20, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.