2 Reis 8

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nísinsin yìí, Eliṣa wí fún obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin jí padà sáyé pé, “Jáde lọ pẹ̀lú ìdílé rẹ kí o sì lọ dúró fún ìgbà díẹ̀ ní ibikíbi tí o bá le dúró sí, nítorí Olúwa ti pàṣẹ ìyàn ní ìlú tí yóò lò tó ọdún méje.”
1 Então, falou Eliseu à mulher de cujo filho ele havia restaurado a vida, dizendo: Levanta-te, e vai, tu e a tua casa, e te hospeda onde quer que conseguires te hospedar; porque o SENHOR chamou uma fome; e ela também sobrevirá à terra por sete anos.
2 Obìnrin náà tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ti sọ. Òun àti ìdílé rẹ̀ sí lọ, wọ́n sì ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọdún méje.
2 E a mulher se levantou, e fez segundo o dizer do homem de Deus; e ela se foi com a sua casa, e se hospedou na terra dos filisteus sete anos.
3 Ní ẹ̀yìn ọdún méje ó sì padà wá láti ilẹ̀ àwọn ará Filistini ó sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba láti lọ bẹ̀ ẹ́ fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
3 E sucedeu, ao fim dos sete anos, que a mulher retornou da terra dos filisteus; e saiu para clamar ao rei pela sua casa e pela sua terra.
4 Ọba sì ń sọ̀rọ̀ sí Gehasi, ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run pé, “Sọ fún mi nípa gbogbo ohun ńlá tí Eliṣa ti ṣe.”
4 E o rei conversou com Geazi, o servo do homem de Deus, dizendo: Conta-me, rogo-te, todas as grandes coisas que Eliseu tem feito.
5 Bí Gehasi ti ń sọ bí tí Eliṣa ṣe jí òkú di alààyè, obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tí Eliṣa ti dá padà sí ayé wá láti bẹ ọba fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
5 E sucedeu, enquanto ele estava contando ao rei como ele havia restaurado à vida um corpo morto, que a mulher a cujo filho ele havia restaurado a vida, clamou ao rei pela sua casa e pela sua terra. E Geazi disse: Meu senhor, ó rei, esta é a mulher, e este é o seu filho, ao qual Eliseu restaurou a vida.
6 Ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà nípa rẹ̀, ó sì sọ fún un.
6 E, quando o rei perguntou à mulher, ela lhe contou. Assim, o rei indicou a ela um certo oficial, dizendo: Restaura tudo o que era dela, e todos os frutos do campo desde o dia em que ela deixou a terra, até este exato momento.
7 Eliṣa lọ sí Damasku, Beni-Hadadi ọba Siria ń ṣe àìsàn. Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba pé, “Ènìyàn Ọlọ́run ti wá láti gbogbo ọ̀nà òkè síbí,”
7 E Eliseu veio até Damasco; e Ben-Hadade, o rei da Síria, estava enfermo; e lhe contaram, dizendo: O homem de Deus veio para cá.
8 ọba sì wí fún Hasaeli pé, “Mú ọrẹ lọ́wọ́ rẹ, sì lọ pàdé ènìyàn Ọlọ́run. Kí o sì béèrè Olúwa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn yìí?”
8 E o rei disse a Hazael: Toma um presente nas tuas mãos, e vai, encontra o homem de Deus e consulta o SENHOR por intermédio dele, dizendo: Recuperar-me-ei desta enfermidade?
9 Hasaeli lọ láti pàdé Eliṣa, ó mú lọ pẹ̀lú rẹ̀ ẹ̀bùn gẹ́gẹ́ bí ogójì ẹrù ìbákasẹ tí gbogbo ìní tí ó dára jù fún wíwò ti Damasku, ó sì wọlé lọ ó sì dúró níwájú rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọ rẹ Beni-Hadadi ọba Siria rán mi láti béèrè pé, ‘Ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn mi yìí?’ ”
9 E foi Hazael ao seu encontro, levando consigo uma oferta e tudo de bom de Damasco, ele carregou em quarenta camelos. Chegou e apresentou-se diante dele, e disse: O teu filho, Ben-Hadade, rei da Síria, enviou-me a ti, dizendo: Recuperar-me-ei desta enfermidade?
10 Eliṣa da á lóhùn pé, “Lọ kí o lọ sọ fún un pé, ‘Ìwo ìbá sàn nítòótọ́’; ṣùgbọ́n Olúwa ti fihàn mí pé nítòótọ́ òun yóò kùú.”
10 E Eliseu disse-lhe: Vai e diz a ele: Tu podes certamente te recuperar; todavia o SENHOR tem me mostrado que ele certamente morrerá.
11 Ó sì ranjú mọ́ ọn pẹ̀lú àtẹjúmọ́ gidigidi títí tí ojú fi ti Hasaeli. Nígbà náà ènìyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
11 E ele descaiu firmemente o seu semblante até que ficou envergonhado; e o homem de Deus chorou.
12 “Kí ni ó dé tí olúwa mi fi ń sọkún?” Hasaeli béèrè.
12 E Hazael disse: Por que chora o meu senhor? E ele respondeu: Como sei o mal que farás aos filhos de Israel; colocarás fogo às suas fortalezas, e matarás os seus moços à espada, despedaçarás os seus filhos, e racharás as suas mulheres grávidas.
13 Hasaeli sì wí pé. “Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ, ajá lásán làsàn yóò ṣe ṣe irú nǹkan ńlá bẹ́ẹ̀?”
13 E Hazael disse: Mas o quê? É o teu servo um cão, para que ele fizesse esta grande coisa? E Eliseu respondeu: O SENHOR tem me mostrado que tu serás rei sobre a Síria.
14 Nígbà náà Hasaeli fi Eliṣa sílẹ̀ ó sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí Beni-Hadadi béèrè, “Kí ni ohun tí Eliṣa sọ fún ọ?” Hasaeli dá a lóhùn, “Ó sọ fún mi wí pé ìwọ yóò sàn nítòótọ́.”
14 Assim, ele partiu de Eliseu, e chegou ao seu mestre; o qual lhe disse: O que te disse Eliseu? E respondeu-lhe: Ele me contou que tu certamente te recuperarias.
15 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì ó mú aṣọ tí ó nípọn, ó sì kì í bọ inú omi ó sì tẹ̀ ẹ́ sí ojú ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú. Nígbà náà Hasaeli sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
15 E sucedeu, no amanhecer, que ele tomou um tecido grosso, e o mergulhou em água, e o estendeu sobre a sua face, de modo que ele morreu; e Hazael reinou em seu lugar.
16 Ní ọdún karùn-ún ti Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli, nígbà tí Jehoṣafati jẹ́ ọba Juda, Jehoramu ọmọ Jehoṣafati bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba Juda.
16 E no quinto ano de Jorão, filho de Acabe, rei de Israel, reinando Josafá, em Judá, começou a reinar Jeorão, filho de Josafá, rei de Judá.
17 Ó jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
17 Tinha ele trinta e dois anos quando começou a reinar; e reinou oito anos em Jerusalém.
18 Ó sì rìn ní ọ̀nà ọba Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti lọ, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu ó sì ṣe ohun búburú níwájú Olúwa.
18 E ele andou no caminho dos reis de Israel, como fez a casa de Acabe; porque a filha de Acabe era sua esposa; e ele fez o mal à vista do SENHOR.
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi. Olúwa kò fẹ́ pa Juda run, ó ti ṣèlérí láti ṣètọ́jú ìmọ́lẹ̀ fún Dafidi àti àwọn ilé rẹ̀ títí láéláé.
19 Contudo, o SENHOR não quis destruir Judá por causa de Davi, o seu servo, já que ele prometeu sempre dar uma luz a ele e aos seus filhos.
20 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
20 Nos seus dias Edom se revoltou contra estar debaixo da mão de Judá, e fizeram um rei sobre si mesmos.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoramu lọ sí Sairi pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Àwọn ará Edomu sì yí i ká àti kẹ̀kẹ́ àwọn olórí wọn, ṣùgbọ́n ó dìde dúró ní òru; àwọn ogun rẹ̀ síbẹ̀síbẹ̀, sá padà lọ ilé.
21 Assim, Jeorão atravessou até Zair, e todas as carruagens com ele; e ele se levantou à noite, e feriu os edomitas, os quais os cercaram, e os capitães das carruagens; e o povo fugiu para dentro das suas tendas.
22 Títí ó fi di òní, Edomu wà nínú ọ̀tẹ̀ lórí Juda, Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkókò kan náà.
22 Contudo, Edom se revoltou contra estar sob a mão de Judá até este dia. Então, Libna se revoltou ao mesmo tempo.
23 Gẹ́gẹ́ bí fún iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Jehoramu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
23 E o restante dos atos de Jeorão, e tudo o que ele fez, não estão escritos no livro das Crônicas dos reis de Judá?
24 Jehoramu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi, Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
24 E Jeorão dormiu com os seus pais, e foi sepultado com os seus pais na cidade de Davi; e Acazias, o seu filho, reinou em seu lugar.
25 Ní ọdún méjìlá Joramu ọmọkùnrin Ahabu ọba Israẹli, Ahasiah ọmọkùnrin Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
25 No décimo segundo ano de Jorão, o filho de Acabe, rei de Israel, Acazias, o filho de Jeorão, rei de Judá, começou a reinar.
26 Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní ọdún kan ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Ataliah, ọmọbìnrin Omri ọba Israẹli.
26 Vinte e dois anos tinha Acazias quando começou a reinar; e ele reinou um ano em Jerusalém. E o nome da sua mãe era Atalia, a filha de Onri, rei de Israel.
27 Nígbà tí ó rin ọ̀nà ilé Ahabu ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí ó tan nípa ìgbéyàwó sí ìdílé Ahabu.
27 E ele andou no caminho da casa de Acabe, e fez o mal à vista do SENHOR, como fez a casa de Acabe; porque ele era o genro da casa de Acabe.
28 Ahasiah sì lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu lọ sí ogun lórí Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Siria ṣẹ́ Joramu lẹ́sẹ̀.
28 E ele foi com Jorão, o filho de Acabe, para a guerra contra Hazael, rei da Síria em Ramote-Gileade; e os sírios feriram Jorão.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Joramu padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí ará Siria ti jẹ ní yà lórí rẹ̀ ní Ramoti ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Aramu.
29 E o rei Jorão voltou a Jezreel para ser curado dos ferimentos que os sírios lhe haviam causado em Ramá, quando ele lutou contra Hazael, rei da Síria. E Acazias, o filho de Jeorão, rei de Judá, desceu para ver Jorão, o filho de Acabe, em Jezreel, porque estava enfermo.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Reis 8, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.