2 Reis 20

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Hesekiah ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò ní í gbádùn.”
1 Naqueles dias Ezequias ficou enfermo de morte. E o profeta Isaías, o filho de Amoz, veio até ele e lhe disse: Assim diz o SENHOR: Põe a tua casa em ordem; porque morrerás e não viverás.
2 Hesekiah yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
2 Então, ele virou a sua face para a parede, e orou ao SENHOR, dizendo:
3 “Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtítọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Hesekiah sọkún kíkorò.
3 Eu te suplico, ó SENHOR, lembra-te agora de como eu tenho caminhado diante de ti em verdade e com um coração perfeito, e tenho feito aquilo que é bom à tua vista. E Ezequias chorou amargamente.
4 Kí ó tó di wí pé Isaiah jáde kúrò ní àárín àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé:
4 E sucedeu que, antes de Isaías ter saído para o meio do pátio, que a palavra do SENHOR veio a ele, dizendo:
5 “Lọ padà kí o sì sọ fún Hesekiah, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dafidi sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò wò ọ́ sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsin yìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
5 Volve-te novamente, e conta a Ezequias, o capitão do meu povo: Assim diz o SENHOR, o Deus de Davi, o teu pai: Ouvi a tua oração e tenho visto as tuas lágrimas; eis que te curarei; no terceiro dia tu subirás para a casa do SENHOR.
6 Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ. Èmi yóò sì gbà ọ́ àti ìlú ńlá yìí láti ọwọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí nítorí ti èmi tìkára mi àti nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi.’ ”
6 E eu acrescentarei aos teus dias quinze anos; e livrarei a ti e a esta cidade da mão do rei da Assíria; e eu defenderei esta cidade por causa de mim mesmo, e por causa do meu servo, Davi.
7 Nígbà náà ni Isaiah wí pé, “Mú odidi ọ̀pọ̀tọ́.” Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fi lé oówo náà, ara rẹ̀ sì yá.
7 E Isaías disse: Toma uma pasta de figos. E eles a tomaram e a colocaram sobre a inflamação, e ele se recuperou.
8 Hesekiah sì béèrè lọ́wọ́ Isaiah pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé Olúwa yóò wò mí sàn àti wí pé èmi yóò lọ sókè sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa láti ọjọ́ kẹta títí di òní?”
8 E Ezequias disse a Isaías: Qual será o sinal de que o SENHOR me curará, e de que eu subirei à casa do SENHOR ao terceiro dia?
9 Isaiah dáhùn pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa fún ọ wí pé Olúwa yóò ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí: kí òjìji lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá, tàbí kí ó padà lọ ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá?”
9 E Isaías disse: Este sinal tu terás do SENHOR, de que o SENHOR fará a coisa que falou: A sombra avançará dez graus, ou retrocederá dez graus?
10 “Ó jẹ́ ohun ìrọ̀rùn fún òjìji láti lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá,” Hesekiah wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí ó lọ padà ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá.”
10 E Ezequias respondeu: É pouca coisa que a sombra desça dez graus; não, mas que a sombra retorne dez graus.
11 Nígbà náà wòlíì Isaiah ké pe Olúwa, Olúwa sì ṣe òjìji padà sí ìgbésẹ̀ mẹ́wàá ó ti sọ̀kalẹ̀ ní òpópó ọ̀nà Ahasi.
11 E Isaías, o profeta, clamou ao SENHOR; e ele trouxe a sombra dez graus para trás, pelos quais ela havia descido no mostrador de Acaz.
12 Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli ránṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Hesekiah nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Hesekiah.
12 Naquele tempo, Merodaque-Baladã, o filho de Baladã, rei de Babilônia, enviou cartas e um presente para Ezequias; porque ele havia ouvido que Ezequias tinha estado enfermo.
13 Hesekiah gba ìránṣẹ́ náà ó sì fihàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò sì fihàn wọ́n.
13 E Ezequias atentou a eles, e mostrou-lhes toda a casa das suas coisas preciosas; a prata, e o ouro, e as especiarias, e os unguentos preciosos, e toda a casa das armas, e tudo o que foi achado nos seus tesouros; não houve nada na sua casa, nem em todo o seu domínio, que Ezequias não tenha lhes mostrado.
14 Nígbà náà Isaiah wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?”
14 Então veio Isaías, o profeta, até ao rei Ezequias, e lhe disse: O que disseram estes homens? E de onde vieram eles a ti? E Ezequias disse: Eles vieram de uma terra longínqua, a saber, de Babilônia.
15 Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?”
15 E ele disse: O que eles viram na tua casa? E Ezequias respondeu: Todas as coisas que estão na minha casa eles viram; não há nada entre os meus tesouros que eu não lhes tenha mostrado.
16 Nígbà náà Isaiah wí fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
16 E Isaías disse a Ezequias: Ouve a palavra do SENHOR.
17 àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ òní, wọn yí ó gbe lọ sí Babeli, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.
17 Eis que vêm dias em que tudo o que estiver na tua casa, e aquilo que os teus pais tiverem acumulado até este dia, será carregado para Babilônia; nada será deixado, diz o SENHOR.
18 Àti díẹ̀ nínú àwọn ìran rẹ, ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀, tí wọn yóò bí fún ọ, ni wọn yóò kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà ní ààfin ọba Babeli.”
18 E dos teus filhos que sairão de ti, aos quais tu gerarás, eles levarão; e eles serão eunucos no palácio do rei de Babilônia.
19 Hesekiah wí fún Isaiah pé. “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò wí pé, “Kò ha dára àlàáfíà àti òtítọ́ ní ọjọ́ ayé mi?”
19 Então, disse Ezequias a Isaías: Boa é a palavra do SENHOR que falaste. E ele disse: Se a paz e a verdade estiverem nos meus dias, não é boa?
20 Ní ti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tókù nípa ìjọba Hesekiah, gbogbo ohun tí ó ṣe tan àti bí ó ti ṣe adágún omi àti ọ̀nà omi náà nípa èyí tí ó gbé wá omi sínú ìlú ńlá, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìgbésẹ̀ ayé àwọn ọba àwọn Juda?
20 E o restante dos atos de Ezequias, e todo o seu poder, e como ele abriu um tanque, e um canal, e trouxe água para dentro da cidade, não estão escritos no livro das Crônicas dos reis de Judá?
21 Hesekiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀: Manase ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
21 E Ezequias dormiu com os seus pais; e Manassés, o seu filho, reinou no seu lugar.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Reis 20, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.