2 Crônicas 35

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Síwájú sí i, Josiah ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa ní Jerusalẹmu, Ọ̀dọ́-àgùntàn àjọ ìrékọjá náà ni wọ́n sì pa ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
1 Além disso, Josias celebrou a páscoa ao SENHOR em Jerusalém; e eles mataram o cordeiro pascal no décimo quarto dia do primeiro mês.
2 Ó sì yàn àwọn àlùfáà sí iṣẹ́ wọn, ó sì gbà wọ́n ní ìyànjú ní ìsìn ilé Olúwa.
2 E ele pôs os sacerdotes nos seus encargos, e os animou no serviço da casa do SENHOR,
3 Ó sì wí fún àwọn ọmọ Lefi, ẹni tí ń kọ́ gbogbo àwọn Israẹli ẹni tí a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa pé ẹ gbé àpótí ẹ̀rí ìyàsọ́tọ̀ sí ilé Olúwa tí Solomoni ọmọ Dafidi ọba Israẹli ti kọ́. Kò gbọdọ̀ jẹ́ ẹrù àgbéká ní èjìká rẹ̀. Nísinsin yìí ẹ sin Olúwa Ọlọ́run yín àti àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
3 e disse aos levitas que ensinavam a todo o Israel, os quais eram consagrados ao SENHOR: Ponde a arca santa na casa que Salomão, o filho de Davi, rei de Israel, edificou; ela não será uma carga sobre os vossos ombros; servi agora ao SENHOR vosso Deus, e o seu povo Israel,
4 Ẹ múra sílẹ̀ nípa ìdílé ní ẹsẹẹsẹ yín gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí a kọ́ láti ọwọ́ Dafidi ọba Israẹli àti gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ Solomoni.
4 e preparai-vos pelas casas dos vossos pais, segundo as vossas turmas, de acordo com o escrito de Davi, rei de Israel, e de acordo com o escrito de Salomão, o seu filho;
5 “Dúró ní ibi mímọ́ pẹ̀lú àkójọpọ̀ àwọn ọmọ Lefi fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìpín àwọn ìdílé àwọn ẹgbẹ́ ará ìlú, àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀.
5 e ponde-vos de pé no santo lugar de acordo com as divisões das famílias dos pais dos vossos irmãos, o povo, e segundo a divisão das famílias dos levitas.
6 Ẹ pa ẹran àjọ ìrékọjá náà, ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kí ẹ sì pèsè ẹran fún àwọn ẹgbẹ́ arákùnrin yín, kí ẹ sì ṣe ohun tí Olúwa paláṣẹ láti ọwọ́ Mose.”
6 Assim, matai o cordeiro pascal, e santificai-vos, e preparai os vossos irmãos, para que eles possam fazer segundo a palavra do SENHOR, dadas pelas mãos de Moisés.
7 Josiah sì pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀ tí ó wà níbẹ̀ iye rẹ̀ jẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (30,000) ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọmọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ìrékọjá, àti pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) akọ màlúù, gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ohun ìní láti ọ̀dọ̀ ọba.
7 E Josias deu ao povo, e a todos os que estavam presentes, cordeiros e cabritos dos rebanhos, ao número de trinta mil, todos para as ofertas da páscoa, e três mil novilhos: estes eram da fazenda do rei.
8 Àwọn ìjòyè rẹ̀ fi tinútinú ta àwọn ènìyàn náà ní ọrẹ àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Hilkiah, Sekariah àti Jehieli, àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run, fún àwọn àlùfáà ní ẹgbẹ̀tàlá (2,600) ẹbọ àjọ ìrékọjá àti ọ̀ọ́dúnrún (300) ẹran ọ̀sìn.
8 E os seus príncipes deram voluntariamente ao povo, aos sacerdotes e aos levitas; Hilquias e Zacarias e Jeiel, soberanos da casa de Deus, deram aos sacerdotes, para a páscoa, dois mil e seiscentos do gado miúdo, e trezentos bois.
9 Àti pẹ̀lú Konaniah àti pẹ̀lú Ṣemaiah àti Netaneli, àti àwọn arákùnrin rẹ̀, àti Haṣabiah, Jeieli àti Josabadi olórí àwọn ọmọ Lefi, ó sì pèsè ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ẹbọ ìrékọjá àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) orí ẹran ọ̀sìn fún àwọn ọmọ Lefi.
9 Também Conanias, e Semaías, e Natanael, os seus irmãos, e Hasabias e Jeiel e Jozabade, chefes dos levitas, deram aos levitas para as ofertas de páscoa, cinco mil do gado miúdo, e quinhentos bois.
10 Nítorí náà, a múra ìsìn náà sílẹ̀, àwọn àlùfáà sì dúró ní ipò wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nípa iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ.
10 Assim, o serviço foi preparado, e os sacerdotes se puseram de pé nos seus lugares, e os levitas nas suas turmas, segundo o mandamento do rei.
11 Ní ti àjọ ìrékọjá a sì pa ẹran, àwọn àlùfáà sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà tí wọ́n gbé sí ọwọ́ wọn, nígbà tí àwọn ọmọ Lefi sì bọ ẹranko.
11 E eles mataram o cordeiro pascal, e os sacerdotes aspergiram o sangue das suas mãos, e os levitas os esfolaram.
12 Wọ́n sì ya àwọn ẹbọ sísun sí apá kan láti fi wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ìdílé àwọn ènìyàn láti rú ẹbọ sí Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé Mose. Wọ́n sì ṣe bákan náà pẹ̀lú àwọn ẹran ọ̀sìn.
12 E eles removeram as ofertas queimadas, para que eles pudessem dar segundo às divisões das famílias do povo, para oferecerem ao SENHOR, como está escrito no livro de Moisés. E assim eles fizeram com os bois.
13 Wọ́n sì fi sun àjọ ìrékọjá lórí iná gẹ́gẹ́ bí ìlànà, wọ́n sì bọ ẹbọ mímọ́ nínú ìkòkò, nínú ọpọ́n àti nínú agbada, wọ́n sì pín wọn kíákíá fún gbogbo àwọn ènìyàn.
13 E eles assaram o cordeiro com fogo de acordo com a ordenança; mas as outras ofertas santas cozeram em potes, e em caldeirões, e em panelas, e prontamente as dividiram entre todo o povo.
14 Lẹ́yìn èyí, wọ́n sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn àlùfáà nítorí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Aaroni, ni wọ́n rú ẹbọ sísun àti ọ̀rá títí di àṣálẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn ọmọ Aaroni àlùfáà.
14 E, posteriormente, eles prepararam para si mesmos, e para os sacerdotes; porque os sacerdotes, os filhos de Arão, estavam ocupados em oferecer as ofertas queimadas e da gordura até a noite; por isso os levitas prepararam para si, e para os sacerdotes, os filhos de Arão.
15 Àwọn akọrin, àwọn ọmọ Asafu, ni wọ́n wà ní ipò wọn tí a sì paláṣẹ fún wọn láti ọwọ́ Dafidi, Asafu, Hemani àti Jedutuni àwọn aríran ọba àti àwọn olùṣọ́nà ní olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà kò gbọdọ̀ fi ojú ọ̀nà wọn sílẹ̀, nítorí àwọn ẹgbẹ́ ọmọ lefi ti múra sílẹ̀ fún wọn.
15 E os cantores, os filhos de Asafe estavam nos seus lugares, de acordo com o mandamento de Davi, e de Asafe, e de Hemã, e de Jedutum, o vidente do rei; e os porteiros serviam em todos os portões; eles não podiam se retirar do seu serviço; porque os seus irmãos, os levitas, preparavam para eles.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àsìkò náà gbogbo àwọn ìsìn Olúwa ni wọ́n gbé jáde fún iṣẹ́ ìrántí àjọ ìrékọjá àti láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ọba Josiah ti pa á láṣẹ.
16 Assim, todo o serviço do SENHOR foi preparado no mesmo dia, para celebrar a páscoa, e para oferecer ofertas queimadas sobre o altar do SENHOR, de acordo com o mandamento do rei Josias.
17 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó gbé kalẹ̀ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá ní àkókò náà àti àjọ àkàrà àìwú fún ọjọ́ méje.
17 E os filhos de Israel que estavam presentes celebraram a páscoa naquele tempo, e a festa dos pães ázimos, sete dias.
18 Àjọ ìrékọjá náà kò sì tí ì sí èyí tí ó dàbí i rẹ̀ ní Israẹli títí dé ọjọ́ wòlíì Samuẹli, kò sì sí ọ̀kan lára àwọn ọba Israẹli tí ó pa irú àjọ ìrékọjá bẹ́ẹ̀ mọ́ gẹ́gẹ́ bí Josiah ti ṣe, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo àwọn Juda àti Israẹli tí ó wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu.
18 E não houve páscoa semelhante àquela guardada em Israel desde os dias de Samuel, o profeta; e nenhum rei de Israel celebrou uma páscoa como celebrou Josias com os sacerdotes, e levitas, e todo o Judá e Israel que estiveram presentes, e os habitantes de Jerusalém.
19 Àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah.
19 No décimo oitavo ano do reinado de Josias foi esta páscoa celebrada.
20 Lẹ́yìn gbogbo èyí nígbà tí Josiah ti tún ilẹ̀ náà ṣetán, Neko ọba Ejibiti gòkè lọ láti bá Karkemiṣi jà lórí odo Eufurate, Josiah sì jáde lọ láti pàdé rẹ̀ ní ibi ìjà.
20 Depois de tudo isto, quando Josias havia preparado o templo, subiu Neco, rei do Egito, para lutar contra Carquemis junto ao Eufrates; e Josias saiu-lhe ao encontro.
21 Ṣùgbọ́n Neko rán ìránṣẹ́ sí i wí pé, “Ìjà wo ni ó ń bẹ láàrín èmi àti ìwọ, ọba Juda? Kì í ṣe ìwọ ni èmi tọ̀ wá ní àkókò yìí, ṣùgbọ́n, ilé pẹ̀lú èyí ti mo bá níjà. Ọlọ́run ti sọ fún mi láti yára àti láti dúró nípa ṣíṣe ìdènà Ọlọ́run, ẹni tí ó wà pẹ̀lú mi, kí òun má bá a pa ọ́ run.”
21 Porém, ele lhe enviou embaixadores, dizendo: Que tenho eu contigo, rei de Judá? Não venho contra ti neste dia, mas contra a casa à qual tenho guerra; porque Deus ordenou-me que me apressasse. Refreia-te de te intrometeres com Deus, que está comigo, não suceda que ele te destrua.
22 Josiah, kò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ara rẹ̀ dà kí ó le bá a jà, kó sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Neko láti ẹnu Ọlọ́run wá, ó sì wá jagun ní àfonífojì Megido.
22 Todavia, Josias não quis desviar a sua face dele, mas disfarçou-se para que pudesse lutar com ele, e não atentou às palavras de Neco, oriundas da boca de Deus, e veio para lutar no vale de Megido.
23 Tafàtafà sì ta ọfà sí ọba Josiah, ó sì sọ fún àwọn ìjòyè pé, “Ẹ gbé mi kúrò, èmi ti gba ọgbẹ́ gidigidi.”
23 E os arqueiros atiraram contra o rei Josias; e o rei disse aos seus servos: Tirai-me daqui; porque estou gravemente ferido.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbé e jáde kúrò nínú kẹ̀kẹ́ náà, wọ́n sì gbé e sínú kẹ̀kẹ́ mìíràn, wọ́n sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, níbi tí ó ti kú, wọ́n sì sin ín sínú ọ̀kan nínú àwọn ibojì àwọn baba rẹ̀, gbogbo Juda àti gbogbo Jerusalẹmu sì ṣọ̀fọ̀ Josiah.
24 Portanto, os seus servos o tiraram da carruagem, e o puseram na segunda carruagem que ele tinha; e o trouxeram para Jerusalém, e ele morreu, e foi sepultado em um dos sepulcros dos seus pais. E todo o Judá e Jerusalém prantearam por Josias.
25 Jeremiah sì pohùnréré ẹkún fún Josiah, gbogbo àwọn akọrin ọkùnrin àti gbogbo àwọn akọrin obìnrin sì ń sọ ti Josiah nínú orin ẹkún wọn ní Israẹli títí di òní. Èyí sì di àṣà ní Jerusalẹmu, a sì kọ ọ́ sínú àwọn orin ẹkún.
25 E Jeremias lamentou por Josias; e todos os cantores e as cantoras falavam de Josias nas suas lamentações até este dia, e lhes fizeram uma ordenança em Israel; e eis que eles estão escritos nas lamentações.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Josiah àti ìwà rere rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a ti kọ sínú ìwé òfin Olúwa.
26 Ora, o restante dos atos de Josias, e a sua bondade, de acordo com aquilo que estava escrito na lei do SENHOR,
27 Gbogbo iṣẹ́ náà, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda.
27 e os seus atos, os primeiros e os últimos, eis que estão escritos no livro dos reis de Israel e de Judá.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Crônicas 35, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.