2 Crônicas 31
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
1 Ora, quando tudo isso estava terminado, todo o Israel que esteve presente saiu para as cidades de Judá, e quebrou as imagens em pedaços, e cortou os bosques, e lançou abaixo os lugares altos e os altares de todo o Judá e Benjamim, em Efraim e também em Manassés, até que destruíram por completo todos eles. Então, todos os filhos de Israel retornaram, cada homem à sua possessão, às suas próprias cidades.
2 Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
2 E Ezequias indicou as turmas dos sacerdotes e dos levitas segundo as suas turmas, cada homem de acordo com o seu serviço, os sacerdotes e os levitas para as ofertas queimadas e para as ofertas de paz, para ministrarem, e para darem graças, e para louvarem nos portões das tendas do SENHOR.
3 Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
3 Também estabeleceu a porção da fazenda do rei para as ofertas queimadas, a saber; para as ofertas queimadas da manhã e da tarde, e para as ofertas queimadas dos shabats, e das luas novas, e para as festas marcadas; como está escrito na lei do SENHOR.
4 Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
4 Além disso, ele ordenou ao povo que habitava em Jerusalém que desse a porção dos sacerdotes e dos levitas, para que eles pudessem se dedicar à lei do SENHOR.
5 Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
5 E tão logo o mandamento se espalhou, os filhos de Israel trouxeram em abundância as primícias do grão, vinho, e azeite, e do mel, e de tudo o que crescia no campo; e o dízimo de todas as coisas trouxeram eles em abundância.
6 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
6 E acerca dos filhos de Israel e de Judá, que habitavam nas cidades de Judá, eles também trouxeram o dízimo dos bois e das ovelhas, e o dízimo das coisas santas as quais foram consagradas ao SENHOR seu Deus, e as depositaram em montões.
7 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
7 No terceiro mês eles começaram a lançar o fundamento dos montões, e as terminaram no sétimo mês.
8 Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
8 E quando vieram Ezequias e os príncipes, e vendo aqueles montões, bendisseram ao SENHOR e ao seu povo Israel.
9 Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
9 Então, Ezequias questionou os sacerdotes e os levitas acerca dos montões.
10 àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
10 E Azarias, o sumo sacerdote da casa de Zadoque respondeu-lhe: Como o povo começou a trazer as ofertas para dentro da casa do SENHOR, temos tido o suficiente para comer, e temos deixado sobra; porque o SENHOR tem abençoado o seu povo; e tem sobrado esta grande provisão.
11 Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
11 Então, Ezequias ordenou que se preparassem câmaras na casa do SENHOR; e eles as prepararam,
12 Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
12 e trouxeram fielmente as ofertas e os dízimos e as coisas consagradas; sobre as quais Conanias, o levita, era governador, e Simei, o seu irmão, era o próximo.
13 Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
13 E Jeiel, e Azarias, e Naate, e Asael, e Jerimote, e Jozabade, e Eliel, e Ismaquias, e Maate, e Benaia eram supervisores sob a mão de Conanias, e Simei, o seu irmão, sob o comando de Ezequias, o rei, e Azarias, o soberano da casa de Deus.
14 Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
14 E Coré, o filho de Imna, o levita, o porteiro do lado leste, estava sobre as ofertas voluntárias a Deus, para distribuir as oblações do SENHOR, e as coisas santíssimas.
15 Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
15 E próximo a ele estavam Éden, e Miniamim, e Jesuá, e Semaías, Amarias, e Secanias, nas cidades dos sacerdotes, nos seus ofícios designados, para dar aos seus irmãos, segundo as suas turmas, tanto aos grandes como aos pequenos;
16 Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
16 além dos que estavam contados pelas genealogias dos homens, da idade de três anos para cima, a todos os que entravam na casa do SENHOR, a sua porção diária, pelo seu ministério nas suas guardas, segundo as suas turmas;
17 Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
17 tanto à genealogia dos sacerdotes, segundo a casa dos seus pais, e dos levitas, de vinte anos de idade em diante, nos seus encargos, segundo as suas turmas;
18 Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
18 e à genealogia de todos os seus pequenos, as suas esposas, e os seus filhos, e as suas filhas, por toda a congregação; porque no seu ofício designado eles se santificavam nas coisas consagradas;
19 Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
19 também para os filhos de Arão, os sacerdotes, os quais estavam nos campos dos arredores das cidades, em cada uma das várias cidades, os homens que foram designados por nome, para dar porções a todos os homens entre os sacerdotes, e a todos que eram considerados pelas genealogias entre os levitas.
20 Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
20 E assim fez Ezequias em todo o Judá, e operou aquilo que era bom, e reto e verdadeiro diante do SENHOR seu Deus.
21 Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.
21 E em toda obra que ele começou no serviço da casa de Deus, e na lei, e nos mandamentos, para buscar o seu Deus, ele o fez de todo o seu coração, e prosperou.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Crônicas 31, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.