2 Crônicas 24

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
1 Joás tinha sete anos de idade quando começou a reinar; e reinou quarenta anos em Jerusalém. E o nome da sua mãe era Zíbia de Berseba.
2 Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
2 E Joás fez aquilo que era reto aos olhos do SENHOR todos os dias de Joiada, o sacerdote.
3 Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
3 E Joiada tomou para ele duas esposas; e ele gerou filhos e filhas.
4 Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
4 E sucedeu depois disso, que Joás estava disposto a reparar a casa do SENHOR.
5 Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
5 E ele reuniu os sacerdotes e os levitas, e disse-lhes: Saí para as cidades de Judá, e reuni de todo o Israel dinheiro para reparar a casa do vosso Deus de ano em ano, e vede para que apressais o negócio. Todavia, os levitas não se apressaram.
6 Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
6 E o rei chamou Joiada, o chefe, e disse a ele: Por que não obrigaste os levitas a trazer de Judá e de Jerusalém a coleta, segundo o mandamento de Moisés, o servo do SENHOR, e da congregação de Israel, para o tabernáculo do testemunho?
7 Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
7 Porque os filhos de Atalia, aquela mulher iníqua, tinham destruído a casa de Deus; e também todas as coisas dedicadas da casa do SENHOR eles entregaram aos baalins.
8 Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
8 E diante da ordem do rei eles fizeram um baú, e o colocaram na parte exterior, junto ao portão da casa do SENHOR.
9 A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
9 E eles fizeram uma proclamação por Judá e Jerusalém para que trouxessem até o SENHOR a coleta que Moisés, o servo de Deus, lançou sobre Israel no deserto.
10 Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
10 E todos os príncipes e todo o povo regozijaram-se, e a trouxeram, e a lançaram dentro do baú, até que terminaram.
11 Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
11 Ora, sucedeu que no momento em que o baú foi trazido para o ofício do rei pelas mãos dos levitas, e vendo que havia muito dinheiro, o escriba do rei e o oficial do sumo sacerdote vinham e esvaziavam o baú, e o tomavam, e o carregavam novamente para o seu lugar. Assim faziam dia após dia, e recolhiam dinheiro em abundância.
12 Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
12 E o rei e Joiada o davam aos que faziam a obra do serviço da casa do SENHOR, e contratavam pedreiros e carpinteiros para repararem a casa do SENHOR, e também aos que confeccionavam ferro e bronze para consertar a casa do SENHOR.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
13 Assim, trabalhavam os oficiais, e a obra era aperfeiçoada por eles, e eles deixaram a casa de Deus no seu estado, e a reforçaram.
14 Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
14 E quando eles a terminaram, trouxeram o restante do dinheiro diante do rei e de Joiada, do qual foram feitos os vasos para a casa do SENHOR, a saber, vasos tanto para se ministrar, como para se oferecer, e colheres, e vasos de ouro e prata. E eles ofereceram ofertas queimadas na casa do SENHOR continuamente, todos os dias de Joiada.
15 Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
15 Todavia, Joiada ficou velho, e cheio de dias quando morreu; e ele tinha cento e trinta anos de idade quando morreu.
16 Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
16 E eles o sepultaram na cidade de Davi, entre os reis, porque ele havia feito o bem em Israel, tanto para com Deus, como para com a sua casa.
17 Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
17 Ora, depois da morte de Joiada vieram os príncipes de Judá, e fizeram reverência ao rei. Então, o rei atentou a eles.
18 Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
18 E eles saíram da casa do SENHOR Deus dos seus pais, e serviram aos bosques e ídolos; e a ira veio sobre Judá e Jerusalém por causa da sua transgressão.
19 Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
19 Contudo, ele enviou profetas entre eles, para trazê-los de volta ao SENHOR; os quais testificaram contra eles; mas eles não quiseram dar ouvido.
20 Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’ ”
20 E o Espírito de Deus veio sobre Zacarias, o filho de Joiada, o sacerdote, o qual se pôs de pé acima do povo, e disse-lhes: Assim diz Deus: Por que transgredis os mandamentos do SENHOR, de modo que não podeis prosperar? Porque vós abandonastes o SENHOR, ele também vos abandonará.
21 Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
21 E conspiraram contra ele, e o apedrejaram com pedras, por mandamento do rei, no átrio da casa do SENHOR.
22 Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
22 Assim o rei Joás não se lembrou da bondade que Joiada, o seu pai, havia-lhe feito, mas matou o seu filho. E, quando morreu, ele disse: O SENHOR olha por isto e o requererá.
23 Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
23 E sucedeu, no fim do ano, que o exército da Síria subiu contra ele; e vieram para Judá e Jerusalém, e destruíram dentre o povo a todos os seus príncipes, e enviaram todo o despojo deles ao rei de Damasco.
24 Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
24 Porque o exército dos sírios veio com uma pequena companhia de homens, e o SENHOR entregou um mui grande exército na sua mão, porque eles haviam abandonado o SENHOR Deus dos seus pais. Assim eles executaram juízo contra Joás.
25 Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
25 E, retirando-se dele (pois em grandes enfermidades o deixaram), os seus próprios servos conspiraram contra ele por causa do sangue dos filhos de Joiada, o sacerdote, e o mataram na sua cama, e ele morreu; e o sepultaram na cidade de Davi, porém não o sepultaram nos sepulcros dos reis.
26 Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
26 E estes são os que conspiraram contra ele: Zabade, o filho de Simeate, a amonita; e Jozabade, o filho de Sinrite, a moabita.
27 Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
27 Ora, quanto a seus filhos, e à grandeza do cargo que foi lançado sobre eles, e à restauração da casa de Deus, eis que estão escritos na história do livro dos reis. Em seu lugar reinou seu filho Amazias.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Crônicas 24, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.