2 Crônicas 21

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
1 Ora, Josafá dormiu com os seus pais, e foi sepultado com os seus pais na cidade de Davi. E Jeorão, o seu filho, reinou no seu lugar.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
2 E tinha irmãos, os filhos de Josafá: Azarias, e Jeiel, e Zacarias, e Azariau, e Micael, e Sefatias; todos estes eram os filhos de Josafá, rei de Israel.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
3 E o seu pai deu-lhes grandes presentes de prata, e de ouro, e de coisas preciosas, assim como cidades fortificadas em Judá; mas o reino ele deu a Jeorão; porque ele era o seu primogênito.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
4 Tendo Jeorão se levantado sobre o reino de seu pai e tendo-se fortificado, matou todos os seus irmãos com a espada, e também diversos príncipes de Israel.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
5 Jeorão tinha trinta e dois anos quando começou a reinar, e reinou oito anos em Jerusalém.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
6 E ele andou no caminho dos reis de Israel, como fez a casa de Acabe; porque teve a filha de Acabe por esposa; e fez aquilo que era mau aos olhos do SENHOR.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
7 Todavia, o SENHOR não quis destruir a casa de Davi, por causa do pacto que ele tinha feito com Davi, e porque prometeu dar uma lâmpada para ele e para os seus filhos para sempre.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
8 Nos seus dias os edomitas se revoltaram por estar debaixo do domínio de Judá, e fizeram para si um rei.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
9 Então, Jeorão saiu com os seus príncipes, e com ele todas as suas carruagens; e ele levantou-se à noite, e feriu os edomitas que o cercavam, e os capitães das suas carruagens.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda.
10 Assim, os edomitas se revoltaram por estar sob a mão de Judá até este dia. Ao mesmo tempo também Libna se revoltou por estar sob a sua mão; porque ele havia abandonado o SENHOR Deus dos seus pais.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
11 Além disso, ele fez lugares altos nos montes de Judá, e fez com que os habitantes de Jerusalém cometessem fornicação, e compeliu Judá a isto.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé,
12 E lhe chegou um escrito de Elias, o profeta, dizendo: Assim diz o SENHOR Deus de Davi, o teu pai: Porque não andastes nos caminhos de Josafá, o teu pai, nem nos caminhos de Asa, rei de Judá,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
13 mas andastes no caminho dos reis de Israel, e fizestes Judá e os habitantes de Jerusalém se prostituir, à semelhança das prostituições da casa de Acabe, e também mataste os teus irmãos, da casa do teu pai, os quais eram melhores do que tu;
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
14 eis que, com uma grande praga o SENHOR ferirá o teu povo, e os teus filhos, e as tuas esposas, e todos os teus bens;
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’ ”
15 e tu terás uma grande enfermidade por um mal nas tuas entranhas, dia após dia, até que em razão da enfermidade, te saiam as tuas entranhas.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
16 Além disso, o SENHOR suscitou contra Jeorão o espírito dos filisteus, e dos árabes, que estavam próximos aos etíopes;
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
17 e eles subiram até Judá, e irromperam e levaram consigo todos os bens que se achou na casa do rei, e também os seus filhos, e as suas esposas; de modo que não lhe restou mais nenhum filho, exceto Jeoacaz, o mais moço dos seus filhos.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
18 E depois de tudo isso, o SENHOR o feriu nas suas entranhas com uma enfermidade incurável.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
19 E sucedeu que, no processo do tempo, ao fim de dois anos, saíram-lhe as entranhas por causa da doença; assim ele morreu dessa grave enfermidade. E o seu povo não lhe queimou como queimara a seus pais.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
20 Trinta e dois anos de idade ele tinha quando começou a reinar; e reinou em Jerusalém por oito anos, e partiu sem ser lembrado. Todavia, eles o sepultaram na cidade de Davi, mas não nos sepulcros dos reis.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Crônicas 21, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.