2 Crônicas 13

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
1 Ora, no décimo oitavo ano do rei Jeroboão, Abias começou a reinar sobre Judá.
2 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah.
2 Ele reinou três anos em Jerusalém. O nome da sua mãe também era Micaía, a filha de Uriel de Gibeá. E houve guerra entre Abias e Jeroboão.
3 Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ (400,000) ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ (800,000) ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
3 E Abias dispôs-se para a peleja com um exército de homens valentes de guerra, a saber, quatrocentos mil homens escolhidos; Jeroboão também pôs a batalha em formação contra ele com oitocentos mil homens escolhidos, sendo homens fortes e valentes.
4 Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
4 E Abias pôs-se de pé sobre o monte Zemaraim, o qual está no monte Efraim, e disse: Ouvi-me, tu Jeroboão, e todo o Israel;
5 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
5 não deveis saber que o SENHOR Deus de Israel deu para sempre o reinado sobre Israel a Davi, de fato a ele e a seus filhos por um pacto de sal?
6 Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
6 Todavia, Jeroboão, o filho de Nebate, o servo de Salomão, filho de Davi, se levantou, e tem se rebelado contra o seu senhor.
7 Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
7 E ajuntaram-se a ele homens vadios os filhos de Belial, e eles se fortaleceram contra Roboão, o filho de Salomão, quando Roboão era jovem e tenro de coração, e não pôde resistir a eles.
8 “Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
8 E, agora vós pensais que podeis resistir ao reino do SENHOR que está nas mãos dos filhos de Davi, e vós sois uma grande multidão, e há convosco bezerros de ouro, os quais Jeroboão vos fez para deuses.
9 Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
9 Não expulsastes vós os sacerdotes do SENHOR, os filhos de Arão, e os levitas, e não fizestes sacerdotes segundo o costume das nações das outras terras? De modo que todo aquele que vier consagrar-se com um novilho e sete carneiros, o mesmo pode ser um sacerdote daqueles que não são deuses.
10 “Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
10 Porém, quanto a nós, o SENHOR é o nosso Deus, e nós não o abandonamos; e os sacerdotes, os quais ministram ao SENHOR, são os filhos de Arão, e os levitas servem nas suas ocupações;
11 Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
11 e eles queimam para o SENHOR toda manhã e toda tarde sacrifícios queimados e incenso aromático; o pão da proposição eles também deixam em ordem sobre a mesa pura; e o candelabro de ouro com as suas lâmpadas, para queimarem toda tarde; porque nós mantemos o encargo do SENHOR nosso Deus; mas vós o abandonastes.
12 Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
12 E, eis que o próprio Deus é conosco por nosso capitão, e os seus sacerdotes com trombetas ressonantes para tocar alarme contra vós. Ó filhos de Israel, não luteis contra o SENHOR Deus dos vossos pais; porque vós não prosperareis.
13 Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
13 Jeroboão, porém, fez com que uma emboscada se formasse na sua retaguarda; assim, eles estavam diante de Judá, e a emboscada estava por detrás deles.
14 Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
14 E quando Judá olhou para trás, eis que a batalha estava na sua dianteira e na sua retaguarda; e eles clamaram ao SENHOR, e os sacerdotes soaram as trombetas.
15 Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
15 Então, os homens de Judá gritaram; e, enquanto os homens de Judá gritavam, sucedeu que Deus feriu Jeroboão e a todo o Israel diante de Abias e de Judá.
16 Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
16 E os filhos de Israel fugiram de diante de Judá; e Deus os entregou nas suas mãos.
17 Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (500,000) ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
17 E Abias e o seu povo os mataram com grande massacre; assim caíram mortos de Israel, quinhentos mil homens escolhidos.
18 Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
18 Assim, os filhos de Israel foram humilhados naquele tempo, e os filhos de Judá prevaleceram, porque eles confiaram no SENHOR Deus dos seus pais.
19 Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
19 E Abias perseguiu Jeroboão, e tomou dele cidades: Betel, com as suas aldeias, e Jesana com as suas aldeias, e Efrom com as suas aldeias.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
20 Jeroboão não voltou a recuperar a força nos dias de Abias; e o SENHOR o feriu, e ele morreu.
21 Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
21 Abias, porém, tornou-se poderoso, e se casou com catorze esposas, e gerou vinte e dois filhos, e dezesseis filhas.
22 Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.
22 E o restante dos atos de Abias, e os seus caminhos, e os seus dizeres, estão escritos na história do profeta Ido.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 2 Crônicas 13, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.