1 Samuel 4
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá.
1 E a palavra de Samuel veio para todo o Israel. Ora, Israel saiu para lutar contra os filisteus, e acampou ao lado de Ebenézer; e os filisteus acamparam em Afeque.
2 Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì (4,000) ọkùnrin nínú ogun náà.
2 E os filisteus colocaram-se em ordem contra Israel; e, quando se engajaram na batalha, Israel foi ferido diante dos filisteus; e eles mataram cerca de quatro mil homens do exército no campo.
3 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
3 E, quando o povo chegou ao campo, os anciãos de Israel disseram: Por que o SENHOR nos feriu hoje diante dos filisteus? Removamos a arca do pacto do SENHOR de Siló até nós para que, quando vier para o meio de nós, possa nos salvar da mão dos nossos inimigos.
4 Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
4 Assim, o povo enviou a Siló, para que trouxessem de lá a arca do pacto do SENHOR dos Exércitos, que habita no meio dos querubins; e os dois filhos de Eli, Hofni e Fineias, lá estavam com a arca do pacto de Deus.
5 Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
5 E, quando a arca do pacto do SENHOR veio para o acampamento, todo o Israel bradou com um grande brado, de modo que a terra voltou a ressoar.
6 Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?”
6 E quando os filisteus ouviram o barulho do brado, disseram: O que significa o barulho deste grande brado no acampamento dos hebreus? E eles compreenderam que a arca do SENHOR havia chegado ao acampamento.
7 àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
7 E os filisteus ficaram temerosos; pois diziam: Deus chegou ao acampamento. E diziam: Ai de nós! Pois até hoje não houve tal coisa.
8 Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
8 Ai de nós! Quem nos livrará da mão destes Deuses poderosos? Estes são os Deuses que feriram os egípcios com todas as pragas no deserto.
9 Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
9 Sejam fortes, e comportai-vos como homens, Ó vós, filisteus, para que não sejais servos dos hebreus, como eles vos foram; comportai-vos como homens, e lutai.
10 Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (30,000) àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
10 E os filisteus lutaram, e Israel foi ferido, e eles fugiram, cada homem para a sua tenda; e houve um massacre mui grande; pois, de Israel, tombaram trinta mil homens a pé.
11 Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
11 E a arca do pacto foi tomada; e os dois filhos de Eli, Hofni e Fineias, foram mortos.
12 Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
12 E ali fugiu do exército um homem de Benjamim, e chegou a Siló no mesmo dia, com as suas vestes rasgadas, e com terra sobre sua cabeça.
13 Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
13 E quando chegou, eis que Eli estava assentado sobre um assento junto à beira do caminho, observando; pois o seu coração tremia pela arca de Deus. E quando o homem adentrou a cidade, e a ela anunciou, toda a cidade irrompeu em brados.
14 Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?”
14 E, quando Eli ouviu o barulho do brado, disse: O que significa o barulho deste tumulto? E o homem entrou apressadamente, e contou a Eli.
15 Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run (98) ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
15 Ora, Eli tinha noventa e oito anos de idade; e os seus olhos estavam turvos, de modo que não conseguia enxergar.
16 Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.”
16 E o homem disse a Eli: Eu sou aquele que saiu do exército, e hoje fugi do exército. E ele disse: O que se fez lá, filho meu?
17 Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
17 E o mensageiro respondeu, e disse: Israel fugiu de diante dos filisteus, e também houve um grande massacre no meio do povo, e também os teus dois filhos, Hofni e Fineias, estão mortos, e a arca de Deus foi tomada.
18 Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
18 E sucedeu, quando ele fez menção da arca de Deus, que ele caiu para trás do assento, ao lado do portão, e o seu pescoço quebrou, e ele morreu; pois era um homem velho e pesado. E ele havia julgado Israel por quarenta anos.
19 Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
19 E a sua nora, a esposa de Fineias, estava com criança, próxima do parto; e quando ela ouviu as notícias de que a arca de Deus fora tomada, e que o seu sogro e o seu marido estavam mortos, ela se curvou e entrou em trabalho de parto; pois suas dores lhe sobrevieram.
20 Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
20 E, chegada a hora da sua morte, as mulheres que estavam de pé junto a ela lhe disseram: Não temas; pois deste à luz um filho. Porém, ela não respondeu, tampouco levou isto em conta.
21 Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
21 E ela deu ao filho o nome de Icabô, dizendo: A glória partiu de Israel; porque a arca de Deus foi tomada, e por causa do seu sogro e do seu marido.
22 Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”
22 E ela disse: A glória partiu de Israel; pois a arca de Deus foi tomada.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Samuel 4, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.