1 Samuel 25

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
1 E Samuel morreu; e todos os israelitas estavam reunidos, e lamentavam por ele, e o sepultaram na sua casa, em Ramá. E Davi se levantou, e desceu ao deserto de Parã.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún (1,000) ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
2 E havia um homem em Maom, cujas posses estavam no Carmelo; e o homem era mui abastado, e tinha três mil ovelhas, e mil cabras; e ele estava tosquiando as suas ovelhas no Carmelo.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
3 Ora, o nome do homem era Nabal, e o nome da sua esposa Abigail; e ela era uma mulher de bom entendimento, e de formosa aparência; mas o homem era grosseiro e mau nas suas ações; e ele era da casa de Calebe.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
4 E Davi ouviu no deserto que Nabal tosquiava as suas ovelhas.
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
5 E Davi enviou dez jovens, e Davi disse aos jovens: Subi ao Carmelo, e ide até Nabal, e saudai-o em meu nome;
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
6 e assim direis àquele que vive em prosperidade: A Paz seja contigo, a paz seja com a tua casa, e a paz seja com tudo o que tens.
7 “ ‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
7 E, ora, tenho ouvido que tu tens tosquiadores: Ora, os teus pastores que estavam conosco, nós não os ferimos, nem houve qualquer coisa que lhes faltasse, todo o tempo em que estiveram no Carmelo.
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’ ”
8 Pergunta aos teus jovens, e eles te mostrarão. Portanto, permite que os jovens encontrem favor em teus olhos; pois chegamos em um bom dia; dá, rogo-te, o que quer que venha à tua mão aos teus servos e ao teu filho Davi.
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
9 E quando os jovens de Davi vieram, eles falaram com Nabal segundo todas estas palavras em nome de Davi, e terminaram.
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
10 E Nabal respondeu aos servos de Davi, e disse: Quem é Davi? E quem é o filho de Jessé? Há muitos servos, atualmente, que rompem, cada qual, com o seu senhor.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
11 Devo eu, portanto, tomar do meu pão, e da minha água, e da minha carne, que matei para os meus tosquiadores, e dar a homens a quem não sei de onde são?
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
12 Assim, os jovens de Davi voltaram no seu caminho, e se foram novamente, e vieram e lhe contaram todos aqueles dizeres.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó (400) ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
13 E Davi disse aos seus homens: Cingi sobre cada homem a sua espada. E eles cingiram sobre cada homem a sua espada; e Davi também cingiu a sua espada; e subiram lá atrás de Davi cerca de quatrocentos homens; e duzentos permaneceram junto aos pertences.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
14 Porém, um dos jovens contou a Abigail, esposa de Nabal, dizendo: Eis que Davi enviou mensageiros do deserto para saudar o nosso senhor; e ele ralhou com eles.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
15 Porém, os homens foram muito bons para conosco, e não fomos feridos, nem nos faltou coisa alguma, contanto que estivéssemos em trato com eles, quando estávamos nos campos.
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
16 Eles eram uma muralha para nós tanto de dia, como de noite; todo o tempo estivemos com eles cuidando das ovelhas.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
17 Agora, portanto, sabe e considera o que farás; pois o mal está determinado contra o nosso senhor, e contra toda a sua casa; pois ele é de tal modo filho de Belial, que um homem não consegue falar com ele.
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
18 Então Abigail se apressou, e pegou duzentos pães, e duas garrafas de vinho, e cinco ovelhas recentemente preparadas, e cinco medidas de cereal tostado, e cem cachos de uvas passas, e duzentos bolos de figos, e os colocou sobre jumentos.
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
19 E ela disse aos seus servos: Segui avante, antes de mim; eis que vou depois de vós. Ela, porém, não contou ao seu marido, Nabal.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
20 E assim foi que, enquanto ela montava o seu jumento, ela desceu pela cobertura do monte, e eis que Davi e os seus homens desceram contra ela; e ela os encontrou.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
21 Ora, Davi havia dito: Certamente, em vão guardei tudo o que este companheiro tem no deserto, de modo que nada faltou de tudo o que lhe pertencia; e ele me retribuiu o bem com o mal.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
22 Assim, e ainda mais, faça Deus aos inimigos de Davi, se eu deixar de tudo o que lhe pertence, pela manhã, qualquer um que mije contra a parede.
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
23 E quando Abigail viu Davi, ela se apressou, e apeou do jumento, e caiu diante de Davi sobre a sua face, e se curvou até o chão,
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
24 e caiu aos seus pés, e disse: Sobre mim, meu senhor, sobre mim deixa esta iniquidade estar: e deixa a tua criada, rogo-te, falar ao teu ouvido, e ouve as palavras da tua criada.
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
25 Rogo-te que o meu senhor não leve em consideração este homem de Belial, a saber, Nabal; pois como é o seu nome, assim é ele: Nabal é o seu nome, e a loucura está com ele; mas eu, tua serva, não vi os jovens do meu senhor, aos quais enviaste.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
26 Agora, portanto, meu senhor, como vive o SENHOR, e como vive a tua alma, visto que o SENHOR te deteve de vir para derramar sangue, e de te vingar a ti mesmo com a tua própria mão; deixa, agora, os teus inimigos e aqueles que buscam o mal ao meu senhor, serem como Nabal.
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
27 E, agora, esta bênção que a tua criada trouxe ao meu senhor, que seja também dada aos jovens que seguem o meu senhor.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
28 Rogo-te que perdoes a transgressão da tua criada; pois o SENHOR certamente fará do meu senhor uma casa segura; porque o meu senhor luta as batalhas do SENHOR, e o mal não foi encontrado em ti em todos os teus dias.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
29 Contudo, um homem se levantou para te perseguir, e para buscar a tua alma; mas a alma do meu senhor estará atada ao fardo da vida com o SENHOR teu Deus; e as almas dos teus inimigos, aquelas ele arremessará por funda, como se do meio de uma funda.
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
30 E sucederá, quando o SENHOR tiver feito ao meu senhor segundo todo o bem que falou a teu respeito, e tiver te indicado soberano sobre Israel;
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
31 que isto não te será por angústia, nem ofensa de coração ao meu senhor, por teres tu derramado sangue sem motivo, ou ter o meu senhor vingado a si mesmo; mas quando o SENHOR tiver lidado bem com o meu senhor, lembra-te, então, da tua criada.
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
32 E Davi disse a Abigail: Bendito seja o SENHOR Deus de Israel, o qual te enviou neste dia para me encontrar;
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
33 e bendito seja o teu conselho, e bendita sejas tu, que me impediste, neste dia, de vir a derramar sangue, e de vingar a mim mesmo com a minha própria mão.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
34 Pois, em verdade, como vive o SENHOR Deus de Israel, o qual me refreou de te ferir, se tu não tivesse se apressado e vindo me encontrar, certamente não teria sobrado a Nabal, pela luz do amanhecer, ninguém que mijasse contra a parede.
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
35 Assim, Davi recebeu da sua mão aquilo que ela havia lhe trazido, e lhe disse: Sobe em paz à tua casa; vê que atentei à tua voz, e aceitei a tua pessoa.
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
36 E Abigail veio a Nabal; e eis que ele fazia um banquete na sua casa, como o banquete de um rei; e o coração de Nabal estava alegre dentro de si, pois ele estava mui embriagado; pelo que ela não lhe contou nada, menos ou mais, até a luz do amanhecer.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
37 Porém, sucedeu pela manhã, quando o vinho saiu de Nabal, e a sua esposa lhe contou estas coisas, que o seu coração morreu dentro dele, e ele se tornou como uma pedra.
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
38 E sucedeu, cerca de dez dias depois, que o SENHOR feriu Nabal, e ele morreu.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.”
39 E, quando Davi ouviu que Nabal estava morto, ele disse: Bendito seja o SENHOR, que pleiteou a causa do meu vexame da mão de Nabal, e guardou o seu servo do mal; pois o SENHOR devolveu a impiedade de Nabal sobre a sua própria cabeça. E Davi mandou buscar e conversou com Abigail, para tomá-la para si por esposa.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
40 E quando os servos de Davi chegaram a Abigail, no Carmelo, eles lhe falaram, dizendo: Davi nos enviou a ti, para te tomar para si por esposa.
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
41 E ela se levantou, e se curvou sobre a sua face até o chão, e disse: Vede, permite que a tua criada seja uma serva para lavar os pés dos servos do meu senhor.
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
42 E Abigail se apressou, e se levantou, e montou em um jumento, com cinco das suas donzelas que iam após ela; e ela foi após os mensageiros de Davi, e se tornou sua esposa.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
43 Davi também tomou Ainoã de Jezreel; e elas também foram, ambas, suas esposas.
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
44 Porém Saul havia dado Mical, sua filha, esposa de Davi, a Palti, filho de Laís, o qual era de Galim.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Samuel 25, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.