1 Samuel 22

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
1 Davi, portanto, partiu dali, e fugiu para a caverna de Adulão; e quando os seus irmãos e toda a casa do seu pai ouviram isto, eles para lá desceram até ele.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó (400) ọmọkùnrin.
2 E todos os que estavam em aflição, e todos os que estavam em dívida, e todos os que estavam descontentes juntaram-se a ele; e ele se tornou capitão sobre eles; e com ele havia cerca de quatrocentos homens.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
3 E Davi foi dali para Mispá de Moabe; e ele disse ao rei de Moabe: Permite, rogo-te, que o meu pai e a minha mãe venham e estejam contigo, até que eu saiba o que Deus fará por mim.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
4 E ele os trouxe diante do rei de Moabe; e eles habitaram com ele todo o período em que Davi esteve na fortificação.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
5 E o profeta Gade disse a Davi: Não permaneças na fortificação; parte, e vai-te à terra de Judá. Então Davi partiu, e adentrou a floresta de Harete.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
6 Quando Saul ouviu que Davi, e os homens que com ele estavam, foram descobertos, (agora Saul permanecia em Gibeá, debaixo de uma árvore em Ramá, tendo em mãos a sua lança, e todos os seus servos estavam com ele);
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
7 então Saul disse aos seus servos que estavam junto a si: Ouvi, agora, vós benjamitas: Dará o filho de Jessé a cada um de vós campos e vinhedos, e fará de vós capitães de milhares, e capitães de centenas;
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
8 para que todos vós tenhais conspirado contra mim, e não haja ninguém que me mostre que o meu filho fez um pacto com o filho de Jessé, e não haja nenhum de vós que esteja condoído por mim, ou me mostre que o meu filho incitou o meu servo contra mim, para estar deitado em espera, como neste dia?
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
9 Então respondeu Doegue, o edomita, o qual estava colocado acima dos servos de Saul, e disse: Eu vi o filho de Jessé vindo a Nobe, a Aimeleque, o filho de Aitube.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
10 E ele consultou o SENHOR por ele, e lhe deu provisões, e lhe deu a espada de Golias, o filisteu.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
11 Então, o rei mandou chamar Aimeleque, o sacerdote, o filho de Aitube, e toda a casa de seu pai, os sacerdotes que estavam em Nobe; e eles vieram todos ao rei.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.”
12 E Saul disse: Ouve, agora, tu, filho de Aitube. E ele respondeu: Aqui estou, meu senhor.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
13 E Saul lhe disse: Por que conspirastes contra mim, tu e o filho de Jessé, ao dar-lhe pão, e uma espada, e teres consultado a Deus por ele, para que ele se levante contra mim, a estar deitado em espera, como neste dia?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
14 Então, Aimeleque respondeu ao rei, e disse: E quem é tão fiel entre todos os teus servos quanto Davi, que é genro do rei, e vai segundo a tua ordem, e é honorável na tua casa?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
15 Comecei eu, então, a consultar Deus por ele? Esteja isto longe de mim; que o rei não impute qualquer coisa ao seu servo, nem a toda a casa do meu pai; pois o teu servo não sabia nada de tudo isso, menos ou mais.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
16 E o rei disse: Certamente morrerás, Aimeleque, tu e toda a casa do teu pai.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.”
17 E o rei disse aos homens da infantaria que estavam junto a ele: Volvei, e matai os sacerdotes do SENHOR; porque a sua mão também está com Davi, e porque eles souberam quando ele fugiu, e não mo mostraram. Porém, os servos do rei não quiseram estender as mãos sobre os sacerdotes do SENHOR.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
18 E o rei disse a Doegue: Volve tu, e cai sobre os sacerdotes. E Doegue, o edomita, volveu, e caiu sobre os sacerdotes, e matou, naquele dia, oitenta e cinco pessoas que vestiam um éfode de linho.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
19 E Nobe, a cidade dos sacerdotes, ele feriu com o fio da espada, tanto homens como mulheres, crianças e lactentes, e bois, e jumentos, e ovelhas, com o fio da espada.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
20 E um dos filhos de Aimeleque, o filho de Aitube, de nome Abiatar, escapou, e fugiu atrás de Davi.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
21 E Abiatar mostrou a Davi que Saul havia matado os sacerdotes do SENHOR.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
22 E Davi disse a Abiatar: Eu soube naquele dia, quando Doegue, o edomita, ali esteve, que ele seguramente contaria a Saul; eu causei a morte de todas as pessoas da casa de teu pai.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
23 Fica tu comigo, não temas; pois aquele que busca a minha vida, busca a tua vida; mas comigo tu estarás salvo.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Samuel 22, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.