1 Samuel 19

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Saulu sọ fún Jonatani ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n pa Dafidi. Ṣùgbọ́n Jonatani fẹ́ràn Dafidi púpọ̀
1 E Saul falou a Jônatas, seu filho, e a todos os seus servos, que eles deveriam matar Davi.
2 Jonatani sì kìlọ̀ fún Dafidi pé, “Baba mi Saulu wá ọ̀nà láti pa ọ́, kíyèsi ara rẹ di òwúrọ̀ ọ̀la; lọ sí ibi ìkọ̀kọ̀, kí o sì sá pamọ́ sí ibẹ̀.
2 Porém, Jônatas, o filho de Saul, agradava-se muito de Davi; e Jônatas falou a Davi, dizendo: Saul, o meu pai procura te matar; agora, portanto, rogo-te, acautela-te até o amanhecer, e permanece em um lugar secreto e te esconde;
3 Èmi yóò jáde lọ láti dúró ní ọ̀dọ̀ baba mi ní orí pápá níbi tí ó wà. Èmi yóò sọ̀rọ̀ fún un nípa à rẹ, èmi yóò sì sọ ohun tí òun bá wí fún ọ.”
3 e eu sairei e permanecerei ao lado do meu pai no campo onde estiveres, e eu conversarei com o meu pai sobre ti; e o que eu vir, isto te contarei.
4 Jonatani sọ̀rọ̀ rere nípa Dafidi fún Saulu baba rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Má ṣe jẹ́ kí ọba kí ó ṣe ohun tí kò dára fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀; nítorí tí kò ṣẹ̀ ọ́, ohun tí ó sì ṣe pé ọ púpọ̀.
4 E Jônatas falou bem de Davi para Saul, o seu pai, e lhe disse: Que o rei não peque contra o teu servo, contra Davi; porque não tem pecado contra ti, e porque as suas obras têm sido muito boas para contigo;
5 Ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu nígbà tí ó pa Filistini. Olúwa ṣẹ́ ogun ńlá fún gbogbo Israẹli, ìwọ rí i inú rẹ dùn. Ǹjẹ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Dafidi aláìṣẹ̀, tí ìwọ yóò fi pa á láìnídìí?”
5 pois ele colocou a sua vida na sua mão, e matou o filisteu, e o SENHOR operou uma grande salvação para todo o Israel; tu o viste e te alegraste; por que, então, pecarás contra sangue inocente ao matar Davi sem um motivo?
6 Saulu fetísí Jonatani, ó sì búra báyìí, “Níwọ́n ìgbà tí Olúwa bá ti ń bẹ láààyè, a kì yóò pa Dafidi.”
6 E Saul atentou à voz de Jônatas; e Saul jurou: Como vive o SENHOR, ele não será morto.
7 Nítorí náà Jonatani pe Dafidi, ó sì sọ gbogbo àjọsọ wọn fún un. Ó sì mú un wá fún Saulu, Dafidi sì wà lọ́dọ̀ Saulu gẹ́gẹ́ bí i ti tẹ́lẹ̀.
7 E Jônatas chamou Davi, e Jônatas lhe mostrou todas aquelas coisas. E Jônatas trouxe Davi até Saul, e ele ficou em sua presença, como em tempos passados.
8 Lẹ́ẹ̀kan an sí i ogun tún wá, Dafidi sì jáde lọ, ó sì bá àwọn ara Filistini jà. Ó sì pa wọn pẹ̀lú agbára, wọ́n sì sálọ níwájú u rẹ̀.
8 E houve guerra novamente; e Davi saiu, e lutou contra os filisteus, e os matou com um grande massacre; e eles fugiram dele.
9 Ṣùgbọ́n ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí orí Saulu bí ó ti jókòó ní ilé e rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Bí Dafidi sì ti fọn ohun èlò orin olókùn,
9 E o espírito maligno da parte do SENHOR esteve sobre Saul, e ele se assentou na sua casa com o seu dardo na mão; e Davi tocava com a sua mão.
10 Saulu sì wá ọ̀nà láti gún un mọ́ ògiri pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Saulu ti ju ọ̀kọ̀ náà mọ́ ara ògiri. Ní alẹ́ ọjọ́ náà Dafidi sì fi ara pamọ́ dáradára.
10 E Saul procurou ferir Davi contra a parede com o dardo; mas ele se desviou da presença de Saul, e ele cravou o dardo na parede; e Davi fugiu, e escapou naquela noite.
11 Saulu rán ènìyàn sí ilé Dafidi láti ṣọ́ ọ kí wọ́n sì pa á ní òwúrọ̀. Ṣùgbọ́n Mikali, ìyàwó Dafidi kìlọ̀ fún un pé, “Tí o kò bá sá fún ẹ̀mí rẹ ní alẹ́ yìí, ní ọ̀la ni a yóò pa ọ́.”
11 Saul também enviou mensageiros à casa de Davi, para observá-lo, e matá-lo pela manhã; e Mical, a esposa de Davi, lhe contou, dizendo: Se não salvares a tua vida esta noite, pela manhã estarás morto.
12 Nígbà náà Mikali sì gbé Dafidi sọ̀kalẹ̀ ó sì fi aṣọ bò ó.
12 Assim, Mical fez Davi descer por uma janela; e ele saiu, e fugiu, e escapou.
13 Mikali gbé ère ó sì tẹ́ e lórí ibùsùn, ó sì fi irun ewúrẹ́ sí ibi orí rẹ̀.
13 E Mical pegou uma imagem, e a deitou na cama, e colocou um travesseiro de pelo de cabra como apoio, e a cobriu com um tecido.
14 Nígbà ti Saulu rán ènìyàn láti lọ fi agbára mú Dafidi, Mikali wí pé, “Ó rẹ̀ ẹ́.”
14 E quando Saul enviou mensageiros para apanharem Davi, ela disse: Ele está enfermo.
15 Nígbà náà ni Saulu rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dafidi ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”
15 E Saul voltou a enviar mensageiros para verem Davi, dizendo: Tragam-mo até mim no leito, para que eu o mate.
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.
16 E quando os mensageiros entraram, eis que havia uma imagem na cama, com um travesseiro de pelo de cabra por apoio.
17 Saulu wí fún Mikali pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀tá mi sálọ tí ó sì bọ́?”
17 E Saul disse a Mical: Por que me enganaste assim, e mandaste embora o meu inimigo, para que escapasse? E Mical respondeu a Saul: Ele me disse: Deixa-me ir, por que deveria eu te matar?
18 Nígbà tí Dafidi ti sálọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama ó sì sọ gbogbo ohun tí Saulu ti ṣe fún un. Òun àti Samuẹli lọ sí Naioti láti dúró níbẹ̀.
18 Assim Davi fugiu, e escapou, e veio até Samuel, a Ramá, e lhe contou tudo o que Saul lhe havia feito. E ele e Samuel foram e habitaram em Naiote.
19 Ọ̀rọ̀ sì tọ Saulu wá pé, “Dafidi wà ní Naioti ní Rama,”
19 E informaram Saul, dizendo: Eis que Davi está em Naiote, em Ramá.
20 Saulu sì rán àwọn ènìyàn láti fi agbára mú Dafidi wá ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Samuẹli dúró níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì wá sórí àwọn arákùnrin Saulu àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀.
20 E Saul enviou mensageiros para apanhar Davi; e quando eles viram a companhia dos profetas profetizando, e Samuel liderando sobre eles, o Espírito de Deus desceu sobre os mensageiros de Saul, e eles também profetizaram.
21 Wọ́n sì sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì rán ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn lọ àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀. Saulu tún rán oníṣẹ́ lọ ní ìgbà kẹta, àwọn náà bẹ̀rẹ̀ sí ní sọtẹ́lẹ̀.
21 E quando isto foi dito a Saul, ele enviou outros mensageiros, e eles profetizaram da mesma forma. E Saul voltou a enviar mensageiros pela terceira vez, e eles também profetizaram.
22 Nígbẹ̀yìn, òun fúnra rẹ̀ sì lọ sí Rama ó sì dé ibi àmù ńlá kan ní Seku. Ó sì béèrè, “Níbo ni Samuẹli àti Dafidi wà?”
22 Ele, então, foi também para Ramá, e chegou a um grande poço que está em Seco; e ele perguntou e disse: Onde estão Samuel e Davi? E foi dito: Eis que eles estão em Naiote, em Ramá.
23 Saulu sì lọ sí Naioti ni Rama. Ṣùgbọ́n, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e lórí ó sì ń lọ lọ́nà, ó sì ń sọtẹ́lẹ̀ títí tí ó fi dé Naioti.
23 E ele foi para lá, a Naiote, em Ramá; e o Espírito de Deus também esteve sobre ele, e ele seguiu adiante, e profetizou, até chegar a Naiote, em Ramá.
24 Ó sì bọ́ aṣọ rẹ̀, òun pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú Samuẹli. Ó sì dùbúlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà àti ní òru. Ìdí nìyìí tí àwọn ènìyàn fi wí pé, “Ṣé Saulu náà wà lára àwọn wòlíì ni?”
24 E ele também se despiu das suas roupas, e profetizou diante de Samuel da mesma forma, e ficou deitado nu aquele dia inteiro e aquela noite inteira. Pelo que eles disseram: Está Saul também entre os profetas?

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Samuel 19, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.