1 Samuel 17

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
1 Ora, os filisteus reuniram os seus exércitos para a batalha, e estavam reunidos em Socó, que pertence a Judá, e acamparam entre Socó e Azeca, em Efes-Damim.
2 Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
2 E Saul e os homens de Israel estavam reunidos, e acamparam junto ao vale de Elá, e ordenaram a batalha contra os filisteus.
3 Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
3 E os filisteus estavam de pé sobre um monte em um lado, e Israel estava de pé em um monte no outro lado; e entre eles havia um vale.
4 Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
4 E ali saiu do acampamento dos filisteus um campeão, chamado Golias, de Gate, cuja altura era seis côvados e um palmo.
5 Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ṣékélì idẹ.
5 E ele tinha um capacete de bronze sobre a sua cabeça, e estava armado com uma capa encouraçada; e o peso da capa era de cinco mil shekels de bronze.
6 Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
6 E ele tinha caneleiras de bronze sobre as suas pernas, e um dardo de bronze entre os seus ombros.
7 Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta (600) kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
7 E a haste da sua lança era como um eixo de tecelão; e a ponta da sua lança pesava seiscentos shekels de ferro; e um que portava um escudo ia diante dele.
8 Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
8 E ele se pôs de pé e gritou aos exércitos de Israel, e disse-lhes: Por que saístes para ordenar a vossa batalha? Não sou eu um filisteu, e vós servos de Saul? Escolhei um homem para vós, e deixai-o descer até mim.
9 Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
9 Se ele for capaz de lutar comigo, e me matar, então seremos vossos servos; mas se eu prevalecer contra ele, e o matar, então vós sereis nossos servos, e nos servireis.
10 Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
10 E o filisteu disse: Eu desafio os exércitos de Israel neste dia; dai-me um homem para que possamos lutar.
11 Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
11 Quando Saul e todos de Israel ouviram aquelas palavras do filisteu, eles ficaram desalentados, e grandemente temerosos.
12 Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
12 Ora, Davi era o filho daquele efrateu de Belém de Judá, cujo nome era Jessé; e ele tinha oito filhos; e o homem seguia entre os homens como um velho nos dias de Saul.
13 Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
13 E os três filhos mais velhos de Jessé foram e seguiram Saul para a batalha; e os nomes dos seus três filhos que foram para a batalha eram Eliabe, o primogênito, e depois dele, Abinadabe, e o terceiro, Samá.
14 Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
14 E Davi era o mais jovem; e os três mais velhos seguiram Saul.
15 ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
15 Davi, porém, foi e retornou de Saul para alimentar as ovelhas do seu pai em Belém.
16 Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
16 E o filisteu se aproximava pela manhã e ao anoitecer, e se apresentou durante quarenta dias.
17 Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
17 E Jessé disse a Davi, o seu filho: Toma agora para os teus irmãos um efa deste cereal tostado e estes dez pães, e corre até o campo aos teus irmãos;
18 Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
18 e carrega estes dez queijos até o capitão de mil, e observa como vão os teus irmãos, e toma deles garantia.
19 Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
19 Ora, Saul e eles, e todos os homens de Israel, estavam no vale de Elá, lutando contra os filisteus.
20 Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
20 E Davi se levantou cedo pela manhã, e deixou as ovelhas com um guardador, e pegou, e foi, como Jessé lhe havia ordenado; e ele veio até a trincheira, quando o exército estava avançando para a luta, e gritava para a batalha.
21 Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
21 Pois Israel e os filisteus haviam ordenado a batalha, exército contra exército.
22 Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
22 E Davi deixou a sua carruagem na mão do guardador da carruagem, e correu para o exército, e veio e saudou os seus irmãos.
23 Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
23 E enquanto ele falava com eles, eis que surgiu ali o campeão, o filisteu de Gate, de nome Golias, dos exércitos dos filisteus, e falou segundo as mesmas palavras; e Davi as ouviu.
24 Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
24 E quando viram o homem, todos os homens de Israel fugiram dele, e ficaram mui temerosos.
25 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
25 E os homens de Israel disseram: Vistes este homem que surgiu? Certamente ele subiu para desafiar Israel; e será que, o homem que o matar, o rei o enriquecerá com grandes riquezas, e lhe dará a sua filha, e fará livre a casa do seu pai em Israel.
26 Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
26 E Davi falou aos homens que estavam junto a ele, dizendo: O que será feito ao homem que matar este filisteu, e remover a vergonha de Israel? Pois, quem é este filisteu incircunciso, para que grite desafio aos exércitos do Deus vivo?
27 Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
27 E o povo lhe respondeu desta maneira, dizendo: Assim será feito ao homem que o matar.
28 Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
28 E Eliabe, seu irmão mais velho, ouviu quando ele falou aos homens; e a ira de Eliabe acendeu-se contra Davi, e ele disse: Por que desceste para cá? E com quem deixaste aquelas poucas ovelhas no deserto? Eu conheço o teu orgulho, e a inconveniência do teu coração; pois desceste para que pudesses ver a batalha.
29 Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
29 E Davi disse: O que fiz eu agora? Não há uma causa?
30 Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
30 E ele se virou dele para outro, e falou da mesma forma; e o povo lhe respondeu novamente da forma anterior.
31 Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
31 E quando as palavras que Davi falou foram ouvidas, eles as relataram diante de Saul; e ele mandou buscá-lo.
32 Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
32 E Davi disse a Saul: Que não falhe o coração de nenhum homem por causa dele; o teu servo irá e lutará contra este filisteu.
33 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
33 E Saul disse a Davi: Tu não estás apto para ir contra este filisteu e contra ele lutar; pois não passas de um jovem, e ele um homem de guerra desde a sua mocidade.
34 Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
34 E Davi disse a Saul: O teu servo cuidava das ovelhas do seu pai, quando apareceu um leão, e um urso, e tomou um cordeiro do rebanho;
35 Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
35 e eu saí atrás dele, e o feri, e o livrei da sua boca; e quando ele se levantou contra mim, eu o peguei pela barba, e o feri, e o matei.
36 Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
36 O teu servo matou tanto o leão, como o urso; e este filisteu incircunciso será como um deles, pois está desafiando os exércitos do Deus vivo.
37 Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.”
37 Além disso, disse Davi: O SENHOR que me livrou da pata do leão, e da pata do urso, livrar-me-á da mão deste filisteu. E Saul disse a Davi: Vai, e o SENHOR seja contigo.
38 Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
38 E Saul armou Davi com a sua armadura, e colocou um capacete de bronze sobre a sua cabeça; também o armou com uma capa encouraçada.
39 Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára.
39 E Davi cingiu a sua espada sobre a sua armadura, e experimentou ir; pois ele não a tinha provado. E Davi disse a Saul: Não posso ir com estas coisas; pois não as provei. E Davi as tirou de si.
40 Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
40 E ele tomou na mão o seu cajado, e escolheu para si cinco pedras lisas do ribeiro, e as colocou em um alforje de pastor que ele tinha, em uma bolsa; e a sua funda estava na sua mão; e ele se aproximou do filisteu.
41 Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
41 E o filisteu avançou e se aproximou de Davi; e o homem que carregava o escudo ia adiante dele.
42 Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
42 E quando o filisteu olhou e viu Davi, ele o desdenhou; pois ele não passava de um jovem, ruivo e de boa aparência.
43 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
43 E o filisteu disse a Davi: Sou eu um cão, para que venhas a mim com varas? E o filisteu amaldiçoou Davi em nome dos seus deuses.
44 Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
44 E o filisteu disse a Davi: Vem até mim, e eu darei a tua carne às aves do céu, e aos animais do campo.
45 Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
45 Então disse Davi ao filisteu: Tu vens a mim com uma espada, e com uma lança, e com um escudo; mas eu vou a ti em nome do SENHOR dos Exércitos, o Deus dos Exércitos de Israel, a quem tu desafiaste.
46 Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
46 Neste dia o SENHOR te entregará na minha mão; e eu te ferirei, e arrancarei de ti a cabeça; e darei as carcaças dos exércitos dos filisteus neste dia para as aves do céu, e para os animais selvagens da terra, para que toda a terra possa saber que há um Deus em Israel.
47 Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
47 E toda esta assembleia saberá que o SENHOR não salva com espada e lança; pois a batalha é do SENHOR, e ele te entregará nas nossas mãos.
48 Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
48 E sucedeu que, quando o filisteu se levantou, e veio e se aproximou para se encontrar com Davi, Davi se apressou e correu em direção ao exército para encontrar o filisteu.
49 Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
49 E Davi pôs a sua mão na sua bolsa, e dali tomou uma pedra, e a atirou, e feriu o filisteu na sua testa, de modo que a pedra afundou-se na sua testa; e ele caiu com a sua face em terra.
50 Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
50 Assim, Davi prevaleceu sobre o filisteu com uma funda e com uma pedra, e feriu o filisteu, e o matou; porém não havia espada na mão de Davi.
51 Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà.
51 Assim Davi correu e se pôs de pé em cima do filisteu, e tomou a sua espada, sacou-a da sua bainha e o matou, e com ela ele cortou sua cabeça. E quando os filisteus viram que o seu campeão estava morto, eles fugiram.
52 Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
52 E os homens de Israel e de Judá levantaram, e gritaram, e perseguiram os filisteus, até chegar ao vale, e aos portões de Ecrom. E os feridos dos filisteus caíram pelo caminho de Saaraim, até Gate e até Ecrom.
53 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
53 E os filhos de Israel retornaram da perseguição aos filisteus, e espoliaram as suas tendas.
54 Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
54 E Davi tomou a cabeça do filisteu, e a trouxe a Jerusalém; mas colocou a sua armadura na sua tenda.
55 Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?”
55 E quando Saul viu Davi avançar contra o filisteu, ele disse a Abner, o capitão do exército: Abner, este jovem é filho de quem? E Abner disse: Como vive a tua alma, ó rei, não sei dizer.
56 Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
56 E o rei disse: Investiga quem é o pai desse rapaz.
57 Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
57 E quando Davi retornava do massacre do filisteu, Abner o tomou, e o trouxe diante de Saul, com a cabeça do filisteu na sua mão.
58 Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?”
58 E Saul lhe disse: De quem tu és filho, jovem homem? E Davi respondeu: Sou filho do teu servo Jessé, o belemita.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Samuel 17, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.