1 Reis 9

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
1 E sucedeu, quando Salomão acabou de edificar a casa do SENHOR, e a casa do rei, e todo o desejo de Salomão, os quais ele se agradou em fazer,
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
2 o SENHOR apareceu a Salomão pela segunda vez, como havia aparecido a ele em Gibeão.
3 Olúwa sì wí fún un pé,
3 E o SENHOR lhe disse: Ouvi a tua oração e a tua súplica, que fizeste diante de mim. Eu consagrei esta casa, que tu edificaste, para ali colocar o meu nome para sempre; e os meus olhos e o meu coração estarão ali perpetuamente.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
4 E se tu andares diante de mim, como Davi, o teu pai, andou, em integridade de coração, e em retidão, para fazer segundo tudo o que te tenho ordenado, e guardares os meus estatutos e os meus juízos;
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
5 então, estabelecerei o trono do teu reino sobre Israel para sempre, como prometi a Davi, o teu pai, dizendo: Não te faltará um homem sobre o trono de Israel.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
6 Se vós, porém, insistirdes em se desviar de me seguir, vós e vossos filhos, e não guardardes os meus mandamentos e os meus estatutos, os quais coloquei diante de vós, mas fordes e servirdes a outros deuses, e os adorardes;
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
7 então, eu cortarei Israel da terra que eu lhes dei; e esta casa, que santifiquei para o meu nome, lançarei da minha vista; e Israel será um provérbio e um escárnio no meio de todo o povo;
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
8 e nesta casa, que é elevada, cada um que passar por ela ficará atônito, e assobiará; e dirão: Por que o SENHOR fez assim à sua terra, e a esta casa?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’ ”
9 E eles responderão: Porque eles abandonaram o SENHOR seu Deus, que retirou os seus pais da terra do Egito, e se apegaram a outros deuses, e os adoraram, e os serviram; portanto, o SENHOR trouxe sobre eles todo este mal.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
10 E sucedeu, ao fim de vinte anos, quando Salomão havia edificado as duas casas, a casa do SENHOR, e a casa do rei,
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
11 (ora, Hirão, o rei de Tiro havia fornecido a Salomão as árvores de cedro e de cipreste, e ouro, segundo todo o seu desejo), que, então, o rei Salomão deu a Hirão vinte cidades na terra da Galileia.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
12 E Hirão saiu de Tiro para ver as cidades que Salomão lhe havia concedido; e elas não lhe agradaram.
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
13 E ele disse: Que cidades são estas que tu me tens concedido, meu irmão? E ele as chamou de terra de Cabul até este dia.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
14 E Hirão enviou ao rei cento e vinte talentos de ouro.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
15 E esta é a razão do tributo que o rei Salomão levantou; para edificar a casa do SENHOR, e a sua própria casa, e Milo, e a muralha de Jerusalém, e Hazor, e Megido e Gezer.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
16 Porque Faraó, o rei do Egito, havia subido, e tomado Gezer, e a queimado com fogo, e matou os cananeus que habitavam na cidade, e a deu como presente à sua filha, esposa de Salomão.
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
17 E Salomão edificou Gezer, e Bete-Horom de baixo.
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
18 E Baalate, e Tadmor no deserto, na terra,
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
19 e todas as cidades de armazenamento que Salomão tinha, e cidades para as suas carruagens, e cidades para os seus cavaleiros, e aquilo que Salomão desejou edificar em Jerusalém, e no Líbano, e em toda a terra do seu domínio.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
20 E todas as pessoas que foram deixadas dos amorreus, heteus, ferezeus, heveus, e jebuseus, os quais não eram dos filhos de Israel,
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
21 os seus filhos que foram deixados depois deles na terra, aos quais os filhos de Israel também não foram capazes de destruir por completo, sobre aqueles Salomão lançou um tributo de trabalho servil até este dia.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
22 Todavia, dos filhos de Israel Salomão não fez servos; no entanto, eles eram homens de guerra, e os seus servos, e os seus príncipes, e os seus capitães, e soberanos das suas carruagens, e dos seus cavaleiros.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta (550), ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
23 Estes eram os chefes dos oficiais que estavam acima do trabalho de Salomão, quinhentos e cinquenta, os quais dominavam sobre o povo que executava a obra.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
24 Contudo, a filha de Faraó subiu da cidade de Davi até a sua casa, que Salomão havia edificado para ela; então edificou a Milo.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
25 E três vezes por ano Salomão oferecia ofertas queimadas e ofertas de paz sobre o altar que ele edificou para o SENHOR, e ele queimou incenso sobre o altar que estava diante do SENHOR. Assim, ele concluiu a casa.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
26 E o rei Salomão fez uma armada de navios em Eziom-Geber, o qual está ao lado de Elate, na costa do mar Vermelho, na terra de Edom.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
27 E Hirão enviou na armada os seus servos, marinheiros que tinham conhecimento do mar, com os servos de Salomão.
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún (420) tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
28 E eles chegaram em Ofir, e retiraram de lá ouro, quatrocentos e vinte talentos, e o trouxeram para o rei Salomão.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Reis 9, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.