1 Reis 4

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
1 Assim, o rei Salomão foi rei sobre todo o Israel.
2 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀:
2 E estes eram os príncipes que ele tinha: Azarias, o filho de Zadoque, o sacerdote,
3 Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé;
3 Eliorefe e Aías, os filhos de Sisa, escribas; Josafá, o filho de Ailude, o cronista.
4 Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun;
4 E Benaia, o filho de Joiada estava sobre o exército; e Zadoque e Abiatar eram os sacerdotes:
5 Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè;
5 e Azarias, o filho de Natã estava sobre os oficiais; e Zabude, o filho de Natã era o oficial-mor, e amigo do rei;
6 Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin;
6 e Aisar estava sobre a casa; e Adonirão, o filho de Abda estava sobre o tributo.
7 Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
7 E Salomão tinha doze oficiais sobre todo o Israel, os quais davam conta das provisões para o rei e sua casa; cada homem fazia a provisão para um mês no ano.
8 Orúkọ wọn ni wọ̀nyí:
8 E estes são os seus nomes: o filho de Hur, no monte Efraim:
9 Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
9 o filho de Dequer, em Macaz, e em Saalabim, e Bete-Semes, e Elom-Bete-Hanã;
10 Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
10 o filho de Hesede, em Arubote; a ele pertencia Socó, e toda a terra de Héfer;
11 Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
11 o filho de Abinadabe, em toda a região de Dor; o qual tinha por esposa a Tafate, a filha de Salomão;
12 Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
12 Baaná, o filho de Ailude; a ele pertencia Taanaque e Megido, e toda Bete-Seã, a qual está junto a Zaretã abaixo de Jezreel, desde Bete-Seã até Abel-Meolá, até o lugar que está além de Jocmeão.
13 Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
13 o filho de Geber, em Ramote-Gileade; a ele pertencia as aldeias de Jair, o filho de Manassés, as quais estão em Gileade; a ele também pertencia a região de Argobe, a qual está em Basã, sessenta cidades grandes com muralhas e barras de bronze;
14 Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
14 Ainadabe, o filho de Ido tinha Maanaim;
15 Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
15 Aimaás estava em Naftali; ele também tomou Basemate, a filha de Salomão, como esposa;
16 Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
16 Baaná, o filho de Husai estava em Aser e em Alote;
17 Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
17 Josafá, o filho de Parua, em Issacar;
18 Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
18 Simei, o filho de Elá, em Benjamim;
19 Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
19 Geber, o filho de Uri estava na região de Gileade, na região de Seom, rei dos amorreus, e de Ogue, rei de Basã; e ele era o único oficial que estava na terra.
20 Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
20 Judá e Israel eram muitos, como a areia que está junto ao mar em multidão, comendo e bebendo, e se alegrando.
21 Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
21 E Salomão reinou sobre todos os reinos, desde o rio até a terra dos filisteus, e até o limite do Egito; eles traziam presentes, e serviram a Salomão todos os dias da sua vida.
22 Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
22 E a provisão de Salomão para um dia era de trinta medidas de farinha fina, e sessenta medidas de alimento,
23 Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
23 dez bois gordos, e vinte bois dos pastos, e uma centena de ovelhas, além de cervos, e cabritos monteses, e corços, e aves cevadas.
24 Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
24 Porquanto ele tinha domínio sobre toda a região neste lado do rio, desde Tifsa até Gaza, sobre todos os reis deste lado do rio; e tinha paz em todos os lados ao seu redor.
25 Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
25 E Judá e Israel habitaram seguros, cada homem debaixo da sua videira e debaixo da sua figueira, desde Dã até Berseba, todos os dias de Salomão.
26 Solomoni sì ní ẹgbàajì (4,000) ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà (12,000) ẹlẹ́ṣin.
26 E Salomão tinha quarenta mil cocheiras de cavalos para as suas carruagens, e doze mil cavaleiros.
27 Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
27 E estes oficiais, cada qual no seu mês, forneciam provisão para o rei Salomão, e para todos os que vinham à mesa do rei Salomão; nada deixavam faltar.
28 Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
28 Também traziam cevada e palha para os cavalos e dromedários, para o local onde os oficiais estavam, cada homem segundo a sua incumbência.
29 Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
29 E Deus deu a Salomão sabedoria e muitíssimo entendimento, e grandeza de coração, como a areia que está à beira do mar.
30 Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
30 E a sabedoria de Salomão sobressaía-se à sabedoria de todos os filhos da região oriental, e toda a sabedoria do Egito.
31 Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
31 Porque ele era mais sábio do que todos os homens; mais do que Etã, o ezraíta, e do que Hemã, e Calcol, e Darda, os filhos de Maol; e a sua fama estava em todas as nações ao redor.
32 Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún (1,005).
32 E ele falou três mil provérbios; e os seus cânticos foram mil e cinco.
33 Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
33 E ele falou das árvores, desde o cedro que está no Líbano até o hissopo que brota da muralha; ele falou também dos animais, e das aves, e dos répteis, e dos peixes.
34 Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.
34 E ali vinham de todos os povos para ouvir da sabedoria de Salomão, de todos os reis da terra, os quais haviam ouvido acerca da sua sabedoria.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Reis 4, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.