1 Reis 12

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
1 E Roboão foi para Siquém; porque todo o Israel havia vindo a Siquém para fazê-lo rei.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
2 Tendo Jeroboão, filho de Nebate, ouvido isto (pois estava ainda no Egito, para onde tinha fugido da presença do rei Salomão, onde habitava,
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
3 e de onde mandaram chamá-lo), veio com toda a congregação de Israel, e falaram a Roboão, dizendo:
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
4 O teu pai fez o nosso jugo doloroso; agora, portanto, faz mais leve o serviço doloroso do teu pai, e o seu jugo pesado que ele pôs sobre nós, e te serviremos.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
5 E ele lhes disse: Parti por mais três dias, depois, retornai a mim. E o povo partiu.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
6 E o rei Roboão consultou os homens velhos, que estavam diante de Salomão, o seu pai, enquanto ele ainda vivia, e disse: Como vós me aconselheis para que eu possa responder a estas pessoas?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
7 E eles lhe falaram, dizendo: Se fores um servo para este povo neste dia, e servi-los, e respondê-los, e falares boas palavras a eles, então, eles serão teus servos para sempre.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
8 Ele, porém, abandonou o conselho dos velhos, o qual eles lhe tinham dado, e consultou os moços que haviam crescido com ele, e que estavam de pé diante dele;
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
9 e disse-lhes: Que conselho vós dais para que nós possamos responder a este povo que falou comigo dizendo: Alivia o jugo que o teu pai pôs sobre nós?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
10 E os moços que haviam crescido com ele lhe falaram, dizendo: Assim falarás a estas pessoas que falaram contigo, dizendo: O teu pai fez pesado o nosso jugo, mas tu o alivia de sobre nós; assim tu dirás a eles: O meu dedo mínimo será mais grosso do que os lombos do meu pai.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
11 E, agora, como o meu pai vos carregou com um jugo pesado, eu acrescentarei ao vosso jugo: o meu pai vos tem castigado com chicote, mas eu vos castigarei com escorpiões.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
12 Assim, Jeroboão e todo o povo vieram até Roboão no terceiro dia, como o rei havia ordenado, dizendo: Retornai a mim no terceiro dia.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
13 E o rei respondeu ao povo de modo áspero, e abandonou o conselho que os velhos lhe tinham dado;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
14 e falou-lhes segundo o conselho dos moços, dizendo: O meu pai fez o vosso jugo pesado, e eu acrescentarei ao vosso jugo; o meu pai também vos castigou com chicotes, mas eu vos castigarei com escorpiões.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
15 Porquanto o rei não atentou ao povo; porque a causa era do SENHOR, que ele pudesse cumprir o seu dizer, o qual o SENHOR falara a Jeroboão, filho de Nebate, por Aías, o silonita.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé,
16 Assim, quando todo o Israel viu que o rei não atentava a eles, o povo respondeu ao rei, dizendo: Que parte temos nós com Davi? Tampouco temos nós herança no filho de Jessé; às vossas tendas, ó Israel; agora olha para a tua própria casa, Davi. Assim, Israel partiu para as suas tendas.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
17 Mas, quanto aos filhos de Israel que habitavam nas cidades de Judá, Roboão reinou sobre eles.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
18 O rei Roboão enviou Adorão, que esteve sobre o tributo; e todo o Israel o apedrejou com pedras, e ele morreu. Por isso, o rei Roboão apressou-se em subir na sua carruagem, para fugir para Jerusalém.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
19 Assim, Israel se rebelou contra a casa de Davi até este dia.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
20 E sucedeu, quando todo o Israel ouviu que Jeroboão havia retornado, que eles mandaram chamá-lo até a congregação, e o fizeram rei sobre todo o Israel; não houve nenhum que seguisse a casa de Davi, senão somente a tribo de Judá.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án (180,000) ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
21 E quando Roboão tinha vindo a Jerusalém, ele reuniu toda a casa de Judá, com a tribo de Benjamim, cento e oitenta mil homens seletos, os quais eram guerreiros, para lutar contra a casa de Israel, para trazer o reino de volta a Roboão, o filho de Salomão.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
22 Contudo, a palavra de Deus veio a Semaías, o homem de Deus, dizendo:
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
23 Fala a Roboão, o filho de Salomão, rei de Judá, e a toda a casa de Judá e Benjamim, e ao remanescente do povo, dizendo:
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.” ’ ” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
24 Assim diz o SENHOR: Não subireis, nem lutareis contra os vossos irmãos, os filhos de Israel; retornai cada homem à sua casa; porquanto esta coisa é da minha parte. Eles, portanto, atentaram à palavra do SENHOR, e retornaram segundo a palavra do SENHOR.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
25 Então, Jeroboão edificou Siquém no monte Efraim, e nela habitou; e saiu dali, e edificou Penuel.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
26 E Jeroboão disse no seu coração: Agora o reino retornará à casa de Davi;
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
27 se este povo subir para fazer sacrifício na casa do SENHOR em Jerusalém, então o coração deste povo retornará ao seu senhor, a saber, a Roboão, rei de Judá, e eles me matarão, e irão novamente a Roboão, rei de Judá.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
28 Assim o rei tomou conselho, e fez dois bezerros de ouro, e lhes disse: É demais para vós subirdes a Jerusalém; eis aqui os teus deuses, ó Israel, os quais te tiraram da terra do Egito.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
29 E ele pôs um em Betel, e o outro pôs em Dã.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
30 E isso se tornou um pecado; pois o povo foi adorar diante de um, a saber, em Dã.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
31 E ele fez uma casa dos lugares altos, e fez sacerdotes dos menores dentre o povo, os quais não eram dos filhos de Levi.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
32 E Jeroboão ordenou uma festa no oitavo mês, no décimo quinto dia do mês, semelhante à festa que existe em Judá, e ele ofereceu sobre o altar. Assim fez em Betel, sacrificando aos novilhos que ele havia feito; e pôs em Betel os sacerdotes dos lugares altos, os quais ele havia feito.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
33 Assim, ele ofereceu sobre o altar que havia feito em Betel no décimo quinto dia do oitavo mês, a saber, no mês que ele havia imaginado no seu próprio coração; e ordenou uma festa para os filhos de Israel; e ofereceu sobre o altar, e queimou incenso.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Reis 12, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.