1 Pedro 4
Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ
1 Ǹjẹ́ bí Kristi ti jìyà fún wa nípa ti ará, irú kan náà ni kí ẹ̀yin fi hámọ́ra; nítorí ẹni tí ó bá ti jìyà nípa ti ara, ó ti bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.
1 Ora, como Cristo padeceu por nós na carne, armai-vos também com o mesmo pensamento, que aquele que sofreu na carne já cessou do pecado.
2 Kí ẹ̀yin má ṣe fi ìgbà ayé yín ìyókù wà nínú ara mọ́ sí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ènìyàn bí kò ṣe sí ìfẹ́ Ọlọ́run.
2 Para que ele não mais viva o resto de seu tempo na carne para as concupiscências dos homens, mas para a vontade de Deus.
3 Nítorí ìgbà tí ó ti kọjá ti tó fún ṣíṣe ìfẹ́ àwọn aláìkọlà, rínrìn nínú ìwà wọ̀bìà, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, ọtí àmupara, ìréde òru, kíkó ẹ̀gbẹ́ ọ̀mùtí, àti ìbọ̀rìṣà tí í ṣe ohun ìríra.
3 Porque o tempo passado de nossa vida, enquanto fazíamos a vontade dos gentios, deve nos bastar, quando andávamos em lascívia, concupiscências, excesso de vinho, orgias, banquetes, e abomináveis idolatrias.
4 Èyí tí ó yà wọ́n lẹ́nu pé ẹ̀yin kò ba wọn súré sínú irú àṣejù ìwà wọ̀bìà wọ́n, tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ yín ní búburú.
4 E acham estranho que não correis com eles no mesmo excesso de dissolução, falando mal de vós;
5 Àwọn ẹni tí yóò jíyìn fún ẹni tí ó ti múra láti ṣe ìdájọ́ alààyè àti òkú.
5 os quais hão de dar conta àquele que está pronto para julgar os vivos e os mortos.
6 Nítorí èyí ní a sá ṣe wàásù ìyìnrere fún àwọn òkú, kí a lè ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nípa ti ara, ṣùgbọ́n kí wọ́n lè wà láààyè si Ọlọ́run nípa tí Ẹ̀mí.
6 Porque por esta causa o evangelho foi pregado também a eles que estão mortos, para que fossem julgados segundo os homens na carne, mas vivessem segundo Deus no espírito.
7 Ṣùgbọ́n òpin ohun gbogbo kù sí dẹ̀dẹ̀; nítorí náà kí ẹ̀yin wà ní àìrékọjá, kí ẹ sì máa ṣọ́ra nínú àdúrà.
7 Mas o fim de todas as coisas está próximo; portanto, sede sóbrios e vigiai em oração.
8 Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tí ó gbóná láàrín ara yín, nítorí ìfẹ́ ni ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
8 Mas, sobretudo, tende ardente caridade entre vós; porque a caridade cobrirá a multidão de pecados.
9 Ẹ máa ṣe ara yín ni àlejò láìsí ìkùnsínú.
9 Sede hospitaleiros uns para com os outros, sem rancor.
10 Bí olúkúlùkù ti rí ẹ̀bùn gbà, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ máa ṣe ìpín fún ni rẹ̀ láàrín ara yín, bí ìríjú rere tí onírúurú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
10 Como cada um recebeu o dom, que ministre o mesmo um ao outro, como bons mordomos da multiforme graça de Deus.
11 Bí ẹnikẹ́ni ba ń sọ̀rọ̀, kí o máa sọ bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bí ẹnikẹ́ni bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí ó ṣe é bí agbára tí Ọlọ́run fi fún un, kí a lè máa yin Ọlọ́run lógo ní ohun gbogbo nípa Jesu Kristi, ẹni tí ògo àti ìjọba wà fún láé àti láéláé. Àmín.
11 Se alguém falar, que fale segundo os oráculos de Deus; se alguém ministrar, deixe-o fazê-lo segundo a habilidade que Deus dá; para que em tudo Deus seja glorificado através de Jesus Cristo, a quem pertencem o louvor e o domínio para sempre e sempre. Amém.
12 Olùfẹ́, ẹ má ṣe ka ìdánwò gbígbóná ti ń bẹ láàrín yín láti dán yín wò bi ẹni pé ohun àjèjì ni ó dé bá yín.
12 Amados, não estranheis a ardente prova que vem a vós para vos testar, como se coisa estranha vos acontecesse.
13 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ̀yin tí jẹ́ alábápín ìyà Kristi, ẹ máa yọ̀, kí ẹ̀yin lè yọ ayọ̀ púpọ̀ nígbà tí a bá fi ògo rẹ̀ hàn.
13 Mas alegrai-vos no fato de serdes participantes dos sofrimentos de Cristo, para que quando sua glória for revelada, também vos regozijeis com excessiva alegria.
14 Bí a bá gàn yín nítorí orúkọ Kristi, ẹni ìbùkún ni yín: nítorí Ẹ̀mí Ògo àti ti Ọlọ́run bà lé yín.
14 Se sois censurados pelo nome de Cristo, felizes sois, porque o Espírito de glória e de Deus repousa sobre vós; por eles, ele é blasfemado, mas por vós, ele é glorificado.
15 Ṣùgbọ́n ẹ má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú yín jìyà bí apànìyàn, tàbí bí olè, tàbí bí olùṣe búburú, tàbí bí ẹni tí ń tojú bọ̀ ọ̀ràn ẹlòmíràn.
15 Mas que nenhum de vós padeça como homicida, ou como ladrão, ou como malfeitor, ou como intrometido em assuntos de outros homens.
16 Ṣùgbọ́n bí ó bá jìyà bí Kristiani kí ojú má ṣe tì í, ṣùgbọ́n kí ó kúkú yin Ọlọ́run lógo nítorí ti o orúkọ yìí.
16 Porém, se algum homem padece como cristão, que não se envergonhe, antes glorifique a Deus nisto.
17 Nítorí ti ìgbà náà dé, tí ìdájọ́ yóò bẹ̀rẹ̀ láti ilé Ọlọ́run wá, bí ó bá sì tètè tí ọ̀dọ̀ wa bẹ̀rẹ̀, ìgbẹ̀yìn àwọn tí kò gba ìyìnrere Ọlọ́run yó ha ti rí?
17 Porque já é chegado o tempo em que o julgamento deve começar pela casa de Deus; e, se primeiro começa por nós, qual será o fim daqueles que não obedecem ao evangelho de Deus?
18 “Bí ó bá ṣe pé agbára káká ni a fi gba olódodo là,
18 E, se o justo dificilmente se salva, onde aparecerá o ímpio e pecador?
19 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwọn tí ń jìyà gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run ni ṣíṣe rere, fi ọkàn wọn lè Ẹlẹ́dàá olóòtítọ́ lọ́wọ́.
19 Portanto, que aqueles que padecem segundo a vontade de Deus possam entregar a guarda de suas almas ao fiel Criador, fazendo o bem.
Atalhos do teclado
- Capítulo anterior←
- Próximo capítulo→
- Versículo anteriork
- Próximo versículoj
- Limpar seleçãoEsc
- Esta ajuda?
Estude este capítulo no WhatsApp
Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Pedro 4, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.