1 Crônicas 5

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
1 Ora, os filhos de Rúben, o primogênito de Israel (pois ele era o primogênito; porém, profanou o leito do seu pai, o seu direito de primogenitura foi dado aos filhos de José, o filho de Israel; e a genealogia não deve ser considerada segundo o seu direito de primogenitura.
2 Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
2 Porque Judá prevaleceu sobre os seus irmãos, e dele provém o líder; mas o direito de primogenitura era de José);
3 àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni:
3 os filhos, digo eu, de Rúben, o primogênito de Israel foram: Enoque, e Palu, Hezrom, e Carmi.
4 Àwọn ọmọ Joẹli:
4 Os filhos de Joel: Semaías, o seu filho; Gogue, o seu filho; Simei, o seu filho,
5 Mika ọmọ rẹ̀,
5 Mica, o seu filho; Reaías, o seu filho; Baal, o seu filho,
6 Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
6 Beera, o seu filho, a quem Tiglate-Pileser, rei da Assíria, levou cativo; ele era príncipe dos rubenitas.
7 Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn:
7 E seus irmãos, pelas suas famílias, quando a genealogia das suas gerações foi considerada, foram os chefes: Jeiel, e Zacarias,
8 àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli.
8 e Belá, o filho de Azaz, o filho de Sema, o filho de Joel, que habitou em Aroer, até Nebo e Baal-Meom,
9 Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
9 e na direção leste, ele habitou até a entrada do deserto, desde o rio Eufrates; porque o seu gado fora multiplicado na terra de Gileade.
10 Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
10 E nos dias de Saul, eles fizeram guerra contra os hagarenos, que caíram pelas suas mãos; e habitaram nas suas tendas por toda parte da terra leste de Gileade.
11 Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
11 E os filhos de Gade habitaram defronte deles, na terra de Basã, até Salca.
12 Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
12 Joel o chefe; e Safã, o imediato; e Janai, e Safate, em Basã.
13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní:
13 E os seus irmãos da casa dos seus pais foram: Micael, e Mesulão, e Seba, e Jorai, e Jacã, e Zia, e Héber; sete.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
14 Estes são os filhos de Abiail, o filho de Huri, o filho de Jaroa, o filho de Gileade, o filho de Micael, o filho de Jesisai, o filho de Jado, o filho de Buz;
15 Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
15 Aí, o filho de Abdiel, o filho de Guni, chefe da casa dos seus pais.
16 Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
16 E eles habitaram em Gileade, em Basã, e nas suas aldeias, e em todos os arredores de Sarom, até os seus limites.
17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
17 Todos estes foram considerados pelas genealogias nos dias de Jotão, rei de Judá, e nos dias de Jeroboão, rei de Israel.
18 Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì (47,760) ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
18 Os filhos de Rúben, e os gaditas, e a meia tribo de Manassés, de homens valentes, homens capazes de empunhar um broquel e espada, e de atirar com arco, e hábeis na guerra, foram quarenta e quatro mil, setecentos e sessenta, que saíam para a guerra.
19 Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
19 E eles fizeram guerra contra os hagarenos, contra Jetur, e Nafis, e Nodabe.
20 Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
20 E foram ajudados contra eles, e os hagarenos foram entregues nas suas mãos, e todos os que estavam com eles; porque clamaram a Deus na batalha, e ele foi suplicado por eles; porque colocaram a sua confiança nele.
21 Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (50,000) àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún (250,000), àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì (2,000), àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún (100,000).
21 E levaram consigo o seu gado; dos seus camelos, cinquenta mil, e das ovelhas, duzentas e cinquenta mil, e dos jumentos, dois mil, e dos homens, cem mil.
22 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
22 Pois ali caíram muitos mortos, porque a guerra era de Deus. E eles habitaram em seus lugares até o cativeiro.
23 Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
23 E os filhos da meia tribo de Manassés habitaram na terra; eles se multiplicaram desde Basã até Baal-Hermom e Senir, e até o monte Hermom.
24 Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
24 E estes foram os cabeças da casa dos seus pais, a saber: Héfer, e Isi, e Eliel, e Azriel, e Jeremias, e Hodavias, e Jadiel, homens fortes e valentes, homens afamados, e cabeças da casa dos seus pais.
25 Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
25 E eles transgrediram contra o Deus dos seus pais, e foram se prostituindo atrás dos deuses do povo da terra, aos quais Deus destruiu diante deles.
26 Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.
26 E o Deus de Israel suscitou o espírito de Pul, rei da Assíria, e o espírito de Tiglate-Pileser, rei da Assíria, e ele os levaram cativos, os rubenitas, e os gaditas, e a meia tribo de Manassés, e os trouxeram até Hala, e Habor, e Hara, e até o rio Gozã, até este dia.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Crônicas 5, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.